-
Léfítíkù 5:11, 12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
11 “‘Tí agbára rẹ̀ ò bá wá ká ẹyẹ oriri méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kó mú ìyẹ̀fun tó kúnná tó jẹ́ ìdá mẹ́wàá òṣùwọ̀n eéfà*+ wá láti fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ torí ẹ̀ṣẹ̀ tó dá. Kó má da òróró sí i, kó má sì fi oje igi tùràrí sí i, torí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni. 12 Kó gbé e wá fún àlùfáà, kí àlùfáà sì bu ẹ̀kúnwọ́ ìyẹ̀fun náà, kó fi ṣe ọrẹ ìṣàpẹẹrẹ,* kó sì mú kó rú èéfín lórí pẹpẹ lórí àwọn ọrẹ àfinásun sí Jèhófà. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
-
-
Léfítíkù 6:14, 15Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
14 “‘Òfin ọrẹ ọkà+ nìyí: Kí ẹ̀yin ọmọ Áárónì mú un wá síwájú Jèhófà, ní iwájú pẹpẹ. 15 Kí ọ̀kan lára wọn bu ẹ̀kúnwọ́ ìyẹ̀fun tó kúnná nínú ọrẹ ọkà àti díẹ̀ lára òróró rẹ̀ àti gbogbo oje igi tùràrí tó wà lórí ọrẹ ọkà, kó sì mú kó rú èéfín lórí pẹpẹ láti mú òórùn dídùn* jáde sí Jèhófà, kó fi ṣe ọrẹ ìṣàpẹẹrẹ.*+
-