ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Wednesday, October 1

Ọgbọ́n tó wá láti òkè . . . ṣe tán láti ṣègbọràn.—Jém. 3:17.

Nígbà míì, ṣé ó máa ń nira fún ẹ láti ṣègbọràn? Ó nira fún Ọba Dáfídì náà láti ṣègbọràn láwọn ìgbà kan, ìdí nìyẹn tó fi gbàdúrà sí Ọlọ́run pé: “Jẹ́ kó máa wù mí láti ṣègbọràn sí ọ.” (Sm. 51:12) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Dáfídì nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, ó máa ń nira fún un láti ṣègbọràn, bọ́rọ̀ tiwa náà sì ṣe rí nìyẹn. Kí nìdí? Ìdí àkọ́kọ́ ni pé àìpé tá a jogún ń mú ká ṣàìgbọràn. Ìkejì, Sátánì máa ń fẹ́ ká ṣọ̀tẹ̀ bíi tiẹ̀. (2 Kọ́r. 11:3) Ìkẹta, ìwà tinú mi ni màá ṣe ló pọ̀ nínú ayé lónìí, ìyẹn ni Bíbélì pè ní “ẹ̀mí tó ń ṣiṣẹ́ nísinsìnyí nínú àwọn ọmọ aláìgbọràn.” (Éfé. 2:2) Torí náà, a gbọ́dọ̀ ṣiṣẹ́ kára láti borí àwọn nǹkan tó lè mú ká dẹ́ṣẹ̀, ká má sì jẹ́ kí Èṣù àti ayé burúkú yìí mú ká ṣàìgbọràn. Àmọ́, ó yẹ ká sapá gan-an láti máa ṣègbọràn sí Jèhófà àtàwọn tó wà nípò àṣẹ. w23.10 6 ¶1

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Thursday, October 2

Wáìnì tó dáa lo gbé pa mọ́ títí di àkókò yìí.—Jòh. 2:10.

Kí la rí kọ́ nínú bí Jésù ṣe sọ omi di wáìnì? Ó kọ́ wa pé ó yẹ ká nírẹ̀lẹ̀. Jésù ò fọ́nnu nítorí iṣẹ́ ìyanu yẹn. Kódà, kò sígbà kankan tí Jésù fọ́nnu nípa àwọn nǹkan tó ṣe. Kàkà bẹ́ẹ̀, ìrẹ̀lẹ̀ tí Jésù ní máa ń jẹ́ kó gbé gbogbo ògo fún Bàbá rẹ̀. (Jòh. 5:​19, 30; 8:28) Táwa náà bá nírẹ̀lẹ̀ bíi ti Jésù, a ò ní máa fọ́nnu nítorí àwọn nǹkan tá à ń gbé ṣe. Kò yẹ ká gbé ògo fún ara wa, kàkà bẹ́ẹ̀, Ọlọ́run tá à ń sìn ló yẹ ká máa yìn torí òun lògo tọ́ sí. (Jer. 9:​23, 24) Ká sòótọ́, kò sí àṣeyọrí tá a lè ṣe láìjẹ́ pé Jèhófà ràn wá lọ́wọ́. (1 Kọ́r. 1:​26-31) Tá a bá nírẹ̀lẹ̀, a ò ní fọ́nnu tá a bá ṣe ohun kan láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́. Ọkàn wa máa balẹ̀ torí a mọ̀ pé Jèhófà rí ohun tá a ṣe, ó sì mọyì ẹ̀. (Fi wé Mátíù 6:​2-4; Héb. 13:16) Torí náà, tá a bá fi hàn pé a nírẹ̀lẹ̀ bíi ti Jésù, ó dájú pé inú Jèhófà máa dùn sí wa.—1 Pét. 5:6. w23.04 4 ¶9; 5 ¶11-12

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Friday, October 3

Ẹ máa wá ire àwọn ẹlòmíì, kì í ṣe tiyín nìkan.—Fílí. 2:4.

Ẹ̀mí Ọlọ́run darí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù láti gba àwọn Kristẹni níyànjú pé kí wọ́n máa ṣe ohun tó máa ṣe àwọn èèyàn láǹfààní. Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé ìmọ̀ràn yìí tá a bá wà nípàdé? Bá a ṣe lè tẹ̀ lé e ni pé ká máa rántí pé àwa nìkan kọ́ ló máa dáhùn nípàdé, ká jẹ́ káwọn ẹlòmíì náà dáhùn. Rò ó wò ná. Tí ìwọ àti ọ̀rẹ́ ẹ kan bá jọ ń sọ̀rọ̀, ṣé ìwọ nìkan ni wàá máa sọ̀rọ̀ ṣáá àbí wàá fún òun náà láǹfààní láti sọ̀rọ̀? Rárá o, wàá jẹ́ kóun náà sọ̀rọ̀! Lọ́nà kan náà, tá a bá wà nípàdé, dípò ká máa nawọ́ ṣáá, á dáa ká jẹ́ káwọn ẹlòmíì náà dáhùn. Kódà, ọ̀kan lára ohun tá a lè ṣe láti gba àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa níyànjú ni pé, ká fún wọn láǹfààní láti dáhùn kí wọ́n lè sọ ohun tí wọ́n gbà gbọ́. (1 Kọ́r. 10:24) Jẹ́ kí ìdáhùn ẹ ṣe ṣókí, káwọn ẹlòmíì lè dáhùn. Tí ìdáhùn ẹ bá tiẹ̀ ṣe ṣókí, má sọ kókó tó pọ̀. Tó o bá sọ gbogbo kókó tó wà nínú ìpínrọ̀ náà, àwọn ará ò ní rí nǹkan kan sọ mọ́. w23.04 22-23 ¶11-13

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́