22 “‘Tí ẹ bá kórè oko yín, ẹ ò gbọ́dọ̀ kárúgbìn eteetí oko yín tán, ẹ má sì ṣa ohun tó bá ṣẹ́ kù lẹ́yìn tí ẹ kórè.+ Kí ẹ fi í sílẹ̀ fún àwọn aláìní*+ àti àjèjì.+ Èmi ni Jèhófà Ọlọ́run yín.’”
19 “Tí o bá kórè oko rẹ, tí o sì gbàgbé ìtí ọkà kan sínú oko, o ò gbọ́dọ̀ pa dà lọ gbé e. Fi sílẹ̀ níbẹ̀ fún àjèjì, ọmọ aláìníbaba àti opó,+ kí Jèhófà Ọlọ́run rẹ lè máa bù kún ọ nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.+