-
Nọ́ńbà 25:7, 8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 Nígbà tí Fíníhásì+ ọmọ Élíásárì ọmọ àlùfáà Áárónì rí i, ojú ẹsẹ̀ ló dìde láàárín àpéjọ náà, ó sì mú ọ̀kọ̀* kan dání. 8 Ló bá tẹ̀ lé ọkùnrin Ísírẹ́lì náà wọnú àgọ́, ó sì gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ, ó gún ọkùnrin Ísírẹ́lì náà àti obìnrin náà níbi ẹ̀yà ìbímọ rẹ̀. Bí àjàkálẹ̀ àrùn tó kọ lu àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe dáwọ́ dúró+ nìyẹn.
-