-
Nọ́ńbà 7:6-9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Mósè wá gba àwọn kẹ̀kẹ́ ẹrù àti màlúù náà, ó sì kó o fún àwọn ọmọ Léfì. 7 Ó fún àwọn ọmọ Gẹ́ṣónì ní kẹ̀kẹ́ ẹrù méjì àti màlúù mẹ́rin, bí wọ́n ṣe nílò rẹ̀ fún iṣẹ́+ wọn; 8 ó sì fún àwọn ọmọ Mérárì ní kẹ̀kẹ́ ẹrù mẹ́rin àti màlúù mẹ́jọ, bí wọ́n ṣe nílò rẹ̀ fún iṣẹ́ wọn, Ítámárì ọmọ àlùfáà Áárónì+ ló ń darí wọn. 9 Àmọ́ kò fún àwọn ọmọ Kóhátì ní ìkankan, torí ojúṣe wọn jẹ mọ́ iṣẹ́ ibi mímọ́,+ èjìká+ ni wọ́n sì máa ń fi ru àwọn ohun mímọ́.
-
-
1 Kíróníkà 15:2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
2 Ìgbà náà ni Dáfídì sọ pé: “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé Àpótí Ọlọ́run tòótọ́ àfi àwọn ọmọ Léfì, nítorí àwọn ni Jèhófà yàn láti máa gbé Àpótí Jèhófà àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ fún òun nígbà gbogbo.”+
-