19 Kò gbọ́dọ̀ sí àpòrọ́ kíkan nínú ilé yín rárá fún ọjọ́ méje, torí tí ẹnikẹ́ni bá jẹ ohun tó ní ìwúkàrà, yálà àjèjì tàbí ọmọ ìbílẹ̀,+ kí ẹ pa* ẹni* yẹn kúrò nínú àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+
48 Tí àjèjì kan bá ń gbé pẹ̀lú yín, tó sì fẹ́ ṣe ayẹyẹ Ìrékọjá láti bọlá fún Jèhófà, kí gbogbo ọkùnrin ilé rẹ̀ dádọ̀dọ́.* Ìgbà yẹn ló lè ṣe ayẹyẹ náà, yóò sì dà bí ọmọ ìbílẹ̀. Àmọ́ aláìdádọ̀dọ́* ò gbọ́dọ̀ jẹ nínú rẹ̀.+