ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 23:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 “Kí o mú èyí tó dáa jù nínú àwọn èso tó kọ́kọ́ pọ́n ní ilẹ̀ rẹ wá sí ilé Jèhófà Ọlọ́run rẹ.+

      “O ò gbọ́dọ̀ se ọmọ ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.+

  • Nọ́ńbà 15:18, 19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 18 “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mò ń mú yín lọ, 19 tí ẹ sì jẹ èyíkéyìí nínú oúnjẹ* ilẹ̀ náà,+ kí ẹ mú ọrẹ wá fún Jèhófà.

  • Nọ́ńbà 18:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Ìwọ náà lo tún ni èyí: àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n mú+ wá pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fífì+ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá mú wá. Mo ti fún ìwọ àtàwọn ọmọkùnrin rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ pẹ̀lú rẹ, kó jẹ́ ìpín+ yín títí lọ. Gbogbo ẹni tó mọ́ nínú ilé rẹ ló lè jẹ ẹ́.+

  • Nọ́ńbà 18:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 “Sọ fún àwọn ọmọ Léfì pé, ‘Ẹ ó máa gba ìdá mẹ́wàá lọ́wọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, èyí tí mo fún yín láti ọwọ́ wọn kó lè jẹ́ ogún+ yín, kí ẹ sì fi ìdá mẹ́wàá lára ìdá mẹ́wàá náà ṣe ọrẹ fún Jèhófà.+

  • Nọ́ńbà 31:28, 29
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 28 Kí o gba ọkàn* kọ̀ọ̀kan nínú ọgọ́rùn-ún márùn-ún (500) èèyàn, ọ̀wọ́ ẹran, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti agbo ẹran lọ́wọ́ àwọn ọmọ ogun tí wọ́n lọ jagun, láti fi ṣe ìpín Jèhófà. 29 Kí ẹ gbà á látinú ìdajì tiwọn, kí ẹ sì fún àlùfáà Élíásárì láti fi ṣe ọrẹ+ fún Jèhófà.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́