15 Torí náà, mo mú àwọn olórí ẹ̀yà yín, àwọn ọkùnrin tó jẹ́ ọlọ́gbọ́n, tí wọ́n sì ní ìrírí, mo yàn wọ́n ṣe olórí yín, olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún, olórí ọgọ́rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, olórí àwọn mẹ́wàá-mẹ́wàá àti àwọn aṣojú nínú àwọn ẹ̀yà yín.+
10 Jóṣúà wá pàṣẹ fún àwọn olórí àwọn èèyàn náà pé: 11 “Ẹ lọ káàkiri ibùdó, kí ẹ sì pa àṣẹ yìí fún àwọn èèyàn náà pé, ‘Ẹ ṣètò oúnjẹ sílẹ̀, torí ní ọjọ́ mẹ́ta òní, ẹ máa sọdá Jọ́dánì láti lọ gba ilẹ̀ tí Jèhófà Ọlọ́run yín fẹ́ fún yín pé kó di tiyín.’”+