-
1 Sámúẹ́lì 13:13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
13 Ni Sámúẹ́lì bá sọ fún Sọ́ọ̀lù pé: “Ìwà òmùgọ̀ lo hù. O ò ṣègbọràn sí àṣẹ tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ pa fún ọ.+ Ká ní o ṣe bẹ́ẹ̀ ni, Jèhófà ì bá fìdí ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Ísírẹ́lì títí láé.
-
-
1 Sámúẹ́lì 15:22, 23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 Sámúẹ́lì wá sọ pé: “Ṣé àwọn ẹbọ sísun àti ẹbọ+ máa ń múnú Jèhófà dùn tó kéèyàn ṣègbọràn sí ohùn Jèhófà? Wò ó! Ṣíṣe ìgbọràn sàn ju ẹbọ,+ fífi etí sílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá+ àgbò; 23 nítorí ẹ̀ṣẹ̀ kan náà ni ìṣọ̀tẹ̀+ àti iṣẹ́ wíwò+ jẹ́, ọ̀kan náà sì ni kíkọjá àyè jẹ́ pẹ̀lú lílo agbára abàmì àti ìbọ̀rìṣà.* Nítorí o ti kọ ọ̀rọ̀ Jèhófà,+ òun náà ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”+
-