25 Ábúráhámù fẹ́ ìyàwó míì, Kétúrà ni orúkọ rẹ̀. 2 Nígbà tó yá, ó bí Símíránì, Jókíṣánì, Médánì, Mídíánì,+ Íṣíbákì àti Ṣúáhì.+
3 Jókíṣánì bí Ṣébà àti Dédánì.
Àwọn ọmọ Dédánì ni Áṣúrímù, Létúṣímù àti Léúmímù.
4 Àwọn ọmọ Mídíánì ni Eéfà, Éférì, Hánókù, Ábíídà àti Élídáà.
Ọmọ Kétúrà ni gbogbo wọn.