-
2 Àwọn Ọba 16:10-13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 Lẹ́yìn náà, Ọba Áhásì lọ pàdé Tigilati-pílésà ọba Ásíríà ní Damásíkù. Nígbà tó rí pẹpẹ tó wà ní Damásíkù, Ọba Áhásì fi àwòrán pẹpẹ náà ránṣẹ́ sí àlùfáà Úríjà, iṣẹ́ ọnà pẹpẹ náà àti bí wọ́n ṣe mọ ọ́n ló wà nínú àwòrán náà.+ 11 Àlùfáà Úríjà+ mọ pẹpẹ+ kan gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìlànà tí Ọba Áhásì fi ránṣẹ́ láti Damásíkù. Àlùfáà Úríjà parí mímọ pẹpẹ náà kí Ọba Áhásì tó dé láti Damásíkù. 12 Nígbà tí ọba dé láti Damásíkù tó sì rí pẹpẹ náà, ó lọ sídìí rẹ̀, ó sì rú àwọn ẹbọ lórí rẹ̀.+ 13 Orí pẹpẹ náà ló ti mú àwọn ẹbọ sísun rẹ̀ àti àwọn ọrẹ ọkà rẹ̀ rú èéfín; ó tún da àwọn ọrẹ ohun mímu rẹ̀ jáde, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ àwọn ẹbọ ìrẹ́pọ̀ rẹ̀ sórí pẹpẹ náà.
-