-
Jẹ́nẹ́sísì 20:6, 7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Ọlọ́run tòótọ́ sọ fún un lójú àlá pé: “Mo mọ̀ pé òótọ́ inú lo fi ṣe ohun tí o ṣe, torí ẹ̀ ni mi ò fi jẹ́ kí o dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyẹn tí mi ò fi jẹ́ kí o fọwọ́ kàn án. 7 Dá ìyàwó ọkùnrin náà pa dà, torí wòlíì+ ni, ó máa bá ọ bẹ̀bẹ̀,+ o ò sì ní kú. Àmọ́ tí o kò bá dá a pa dà, ó dájú pé wàá kú, ìwọ àti gbogbo àwọn tó jẹ́ tìrẹ.”
-
-
Mátíù 27:19Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
19 Bákan náà, nígbà tó jókòó sórí ìjókòó ìdájọ́, ìyàwó rẹ̀ ránṣẹ́ sí i pé: “Má ṣe ní ohunkóhun ṣe pẹ̀lú ọkùnrin olódodo yẹn, torí mo jìyà gan-an lójú àlá lónìí nítorí rẹ̀.”
-