25 Ó dájú pé o ò ní hùwà báyìí, pé kí o pa olódodo pẹ̀lú ẹni burúkú, tó fi jẹ́ pé ohun kan náà+ ló máa ṣẹlẹ̀ sí olódodo àti ẹni burúkú! Ó dájú pé o ò ní ṣe bẹ́ẹ̀.+ Ṣé Onídàájọ́ gbogbo ayé kò ní ṣe ohun tó tọ́ ni?”+
7 Ẹ jẹ́ kí ìbẹ̀rù Jèhófà wà lọ́kàn yín.+ Ẹ máa kíyè sára nípa ohun tí ẹ̀ ń ṣe, nítorí pé kò sí àìṣẹ̀tọ́,+ kò sí ojúsàájú,+ bẹ́ẹ̀ ni kò sí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ́dọ̀ Jèhófà Ọlọ́run wa.”+