20 Míríámù wòlíì obìnrin, ẹ̀gbọ́n Áárónì wá mú ìlù tanboríìnì, gbogbo obìnrin sì ń jó tẹ̀ lé e pẹ̀lú ìlù tanboríìnì. 21 Míríámù fi orin dá àwọn ọkùnrin lóhùn pé:
“Ẹ kọrin sí Jèhófà, torí ó ti di ẹni àgbéga.+
Ó taari ẹṣin àti ẹni tó gùn ún sínú òkun.”+