-
Dáníẹ́lì 4:30-32Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
30 Ọba ń sọ pé: “Ṣebí Bábílónì Ńlá nìyí, tí mo fi agbára mi àti okun mi kọ́ fún ilé ọba àti fún ògo ọlá ńlá mi?”
31 Ọba ò tíì sọ̀rọ̀ yìí tán lẹ́nu tí ohùn kan fi dún láti ọ̀run pé: “À ń sọ fún ìwọ Ọba Nebukadinésárì pé, ‘Ìjọba náà ti kúrò lọ́wọ́ rẹ,+ 32 wọ́n sì máa lé ọ kúrò láàárín àwọn èèyàn. Ọ̀dọ̀ àwọn ẹranko ni wàá máa gbé, a máa fún ọ ní ewéko jẹ bí akọ màlúù, ìgbà méje sì máa kọjá lórí rẹ, títí o fi máa mọ̀ pé Ẹni Gíga Jù Lọ ni Alákòóso nínú ìjọba aráyé, ẹni tó bá sì wù ú ló ń gbé e fún.’”+
-