-
Jeremáyà 31:35, 36Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
35 Ohun tí Jèhófà sọ nìyí,
Ẹni tó ń mú kí oòrùn máa tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán,
Tó sì ṣe òfin* pé kí òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ máa tàn ní òru,
Ẹni tó ń ru òkun sókè, tó sì ń mú kí ìgbì rẹ̀ máa pariwo,
Ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun:+
36 “‘Bí àwọn ìlànà yìí bá yí pa dà
Nìkan ni àtọmọdọ́mọ Ísírẹ́lì kò fi ní jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi mọ́,’ ni Jèhófà wí.”+
-
-
Jónà 1:4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
4 Lẹ́yìn náà, Jèhófà mú kí ìjì kan tó lágbára jà lórí òkun, ìjì náà sì le débi pé ọkọ̀ náà fẹ́rẹ̀ẹ́ ya.
-