2 “‘Tàbí tí ẹnì* kan bá fara kan ohun àìmọ́ èyíkéyìí, yálà òkú ẹran inú igbó tó jẹ́ aláìmọ́, ẹran ọ̀sìn tó jẹ́ aláìmọ́ tàbí ọ̀kan lára àwọn ohun alààyè tó ń gbá yìn-ìn tó jẹ́ aláìmọ́,+ ẹni náà máa di aláìmọ́, á sì jẹ̀bi, kódà tí kò bá tiẹ̀ mọ̀.
23 “‘Kí wọ́n fún àwọn èèyàn mi ní ìtọ́ni nípa ìyàtọ̀ tó wà láàárín ohun tó mọ́ àti ohun yẹpẹrẹ; wọ́n á sì kọ́ wọn ní ìyàtọ̀ tó wà láàárín ohun tí kò mọ́ àti ohun tó mọ́.+