ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 40:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  9 Lọ sórí òkè tó ga,

      Ìwọ obìnrin tó ń mú ìròyìn ayọ̀ wá fún Síónì.+

      Gbé ohùn rẹ sókè tagbáratagbára,

      Ìwọ obìnrin tó ń mú ìròyìn ayọ̀ wá fún Jerúsálẹ́mù.

      Gbé e sókè, má bẹ̀rù.

      Kéde fún àwọn ìlú Júdà pé: “Ọlọ́run yín rèé.”+

  • Jeremáyà 31:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Wọ́n á wá, wọ́n á sì kígbe ayọ̀ ní ibi gíga Síónì+

      Inú wọn á dùn nítorí oore* Jèhófà,

      Nítorí ọkà àti wáìnì tuntun+ pẹ̀lú òróró,

      Nítorí àwọn ọmọ inú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran.+

      Wọ́n* á dà bí ọgbà tí a bomi rin dáadáa,+

      Wọn kò sì ní ráágó mọ́.”+

  • Jeremáyà 33:10, 11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 “Ohun tí Jèhófà sọ nìyí, ‘Ní ibí yìí tí ẹ̀ ń sọ pé ó jẹ́ aṣálẹ̀, tí kò sí èèyàn tàbí ẹran ọ̀sìn níbẹ̀, ní àwọn ìlú Júdà àti àwọn ojú ọ̀nà Jerúsálẹ́mù tó ti di ahoro, tí kò sí èèyàn tàbí ẹni tó ń gbé ibẹ̀ àti ẹran ọ̀sìn, ibẹ̀ ni a ó tún ti pa dà gbọ́ 11 ìró ayọ̀ àti ìró ìdùnnú,+ ohùn ọkọ ìyàwó àti ohùn ìyàwó, ohùn àwọn tó ń sọ pé: “Ẹ fi ọpẹ́ fún Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, nítorí Jèhófà jẹ́ ẹni rere;+ ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì wà títí láé!”’+

      “‘Wọ́n á mú ẹbọ ìdúpẹ́ wá sínú ilé Jèhófà,+ nítorí màá mú àwọn tí wọ́n kó lọ sí oko ẹrú láti ilẹ̀ náà pa dà wá bíi ti ìbẹ̀rẹ̀,’ ni Jèhófà wí.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́