ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 15:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  11 Jèhófà, ta ló dà bí rẹ nínú àwọn ọlọ́run?+

      Ta ló dà bí rẹ, ìwọ tí o fi hàn pé ẹni mímọ́ jù lọ ni ọ́?+

      Ẹni tó yẹ ká máa bẹ̀rù, ká máa fi orin yìn, Ẹni tó ń ṣe ohun ìyanu.+

  • 2 Àwọn Ọba 19:22-24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 22 Ta lo pẹ̀gàn, tí o sì sọ̀rọ̀ òdì sí?+

      Ta lo gbé ohùn rẹ sókè sí,+

      Tí o sì gbé ojú rẹ ga sí?

      Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì mà ni!+

      23 O tipasẹ̀ àwọn òjíṣẹ́ rẹ+ pẹ̀gàn Jèhófà,+ o sọ pé,

      ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn kẹ̀kẹ́ ogun mi,

      Màá gun ibi gíga àwọn òkè,

      Ibi tó jìnnà jù lọ ní Lẹ́bánónì.

      Ṣe ni màá gé àwọn igi kédárì rẹ̀ tó ga fíofío lulẹ̀, àwọn ààyò igi júnípà rẹ̀.

      Màá wọ ìpẹ̀kun ibi tó máa ń sá sí, igbó kìjikìji rẹ̀.

      24 Màá gbẹ́ kànga, màá sì mu àjèjì omi;

      Màá fi àtẹ́lẹsẹ̀ mi mú kí gbogbo odò* Íjíbítì gbẹ.’

  • Àìsáyà 10:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Ní ọjọ́ yẹn, àwọn tó ṣẹ́ kù ní Ísírẹ́lì

      Àti àwọn tó yè bọ́ ní ilé Jékọ́bù

      Kò tún ní gbára lé ẹni tó lù wọ́n;+

      Àmọ́ wọ́n máa fi òtítọ́ gbára lé Jèhófà,

      Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì.

  • Ìsíkíẹ́lì 39:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Màá mú kí àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì mọ orúkọ mímọ́ mi, mi ò sì tún ní jẹ́ kí wọ́n kó ẹ̀gàn bá orúkọ mímọ́ mi mọ́; àwọn orílẹ̀-èdè á sì wá mọ̀ pé èmi ni Jèhófà,+ Ẹni Mímọ́ ní Ísírẹ́lì.’+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́