22 Ọmọ ọdún mẹ́jọ ni Jòsáyà+ nígbà tó jọba, ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n (31) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Jédídà ọmọ Ádáyà láti Bósíkátì.+ 2 Ó ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Jèhófà, ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Dáfídì baba ńlá rẹ̀,+ kò sì yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.