-
Diutarónómì 28:15Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 “Àmọ́ tí o ò bá pa gbogbo àṣẹ àti òfin Jèhófà Ọlọ́run rẹ mọ́, èyí tí mò ń pa láṣẹ fún ọ lónìí, láti fi hàn pé ò ń fetí sí ohùn rẹ̀, gbogbo ègún yìí máa wá sórí rẹ, ó sì máa bá ọ:+
-
-
Jóṣúà 23:15, 16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 Àmọ́ bí gbogbo ìlérí tó dáa tí Jèhófà Ọlọ́run yín ṣe fún yín ṣe ṣẹ sí yín lára,+ bẹ́ẹ̀ ni Jèhófà máa mú gbogbo àjálù tó ṣèlérí* wá sórí yín, ó sì máa pa yín run lórí ilẹ̀ dáradára tí Jèhófà Ọlọ́run yín fún yín.+ 16 Tí ẹ bá da májẹ̀mú Jèhófà Ọlọ́run yín tó pa láṣẹ pé kí ẹ máa pa mọ́, tí ẹ bá sì lọ ń sin àwọn ọlọ́run míì, tí ẹ̀ ń forí balẹ̀ fún wọn, Jèhófà máa bínú sí yín gidigidi,+ ẹ sì máa pa run kíákíá lórí ilẹ̀ dáradára tó fún yín.”+
-