15 Nítorí ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ fún mi nìyí: “Gba ife wáìnì ìbínú yìí ní ọwọ́ mi, kí o sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo bá rán ọ sí mu ún. 16 Wọ́n á mu, wọ́n á ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n, wọ́n á sì máa ṣe bíi wèrè nítorí idà tí màá rán sí àárín wọn.”+