-
Jeremáyà 8:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Jèhófà sọ pé: “Ní àkókò yẹn, wọ́n á kó egungun àwọn ọba Júdà àti egungun àwọn ìjòyè rẹ̀, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì pẹ̀lú egungun àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù jáde kúrò nínú sàréè wọn. 2 A ó dà wọ́n síta lábẹ́ oòrùn, òṣùpá àti lábẹ́ gbogbo ọmọ ogun ọ̀run tí wọ́n nífẹ̀ẹ́, tí wọ́n jọ́sìn, tí wọ́n tẹ̀ lé, tí wọ́n wá, tí wọ́n sì forí balẹ̀ fún.+ A ò ní kó wọn jọ, bẹ́ẹ̀ ni a ò ní sin wọ́n. Wọn á dà bí ajílẹ̀ lórí ilẹ̀.”+
-
-
Sefanáyà 1:4, 5Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
4 “Màá na ọwọ́ mi sórí Júdà
Àti sórí gbogbo àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù,
Gbogbo àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn tó ń sin* Báálì+ ní ibí yìí ni màá sì pa rẹ́,
Àti orúkọ àwọn àlùfáà ọlọ́run àjèjì pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn àlùfáà míì,+
5 Àti àwọn tó ń forí balẹ̀ lórí òrùlé fún àwọn ọmọ ogun ọ̀run+
Àti àwọn tó ń forí balẹ̀, tí wọ́n ń jẹ́jẹ̀ẹ́ pé ti Jèhófà+ làwọn ń ṣe
Lẹ́sẹ̀ kan náà, tí wọ́n ń jẹ́jẹ̀ẹ́ pé ti Málíkámù làwọn ń ṣe;+
-