14 Torí ilẹ̀ ló máa ń fi ẹyin rẹ̀ sí,
Ó sì ń mú kí wọ́n móoru nínú iyẹ̀pẹ̀.
15 Ó gbàgbé pé àwọn ẹsẹ̀ kan lè tẹ̀ wọ́n fọ́,
Tàbí pé ẹran igbó lè tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.
16 Ó ń ṣe àwọn ọmọ rẹ̀ ṣúkaṣùka, bí ẹni pé òun kọ́ ló bí wọn;+
Kò bẹ̀rù pé làálàá òun lè já sí asán.