-
Dáníẹ́lì 4:31-33Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
31 Ọba ò tíì sọ̀rọ̀ yìí tán lẹ́nu tí ohùn kan fi dún láti ọ̀run pé: “À ń sọ fún ìwọ Ọba Nebukadinésárì pé, ‘Ìjọba náà ti kúrò lọ́wọ́ rẹ,+ 32 wọ́n sì máa lé ọ kúrò láàárín àwọn èèyàn. Ọ̀dọ̀ àwọn ẹranko ni wàá máa gbé, a máa fún ọ ní ewéko jẹ bí akọ màlúù, ìgbà méje sì máa kọjá lórí rẹ, títí o fi máa mọ̀ pé Ẹni Gíga Jù Lọ ni Alákòóso nínú ìjọba aráyé, ẹni tó bá sì wù ú ló ń gbé e fún.’”+
33 Ní ìṣẹ́jú yẹn, ọ̀rọ̀ náà ṣẹ sí Nebukadinésárì lára. Wọ́n lé e kúrò láàárín àwọn èèyàn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ ewéko bí akọ màlúù, ìrì ọ̀run sẹ̀ sí i lára, títí irun rẹ̀ fi gùn bí ìyẹ́ idì, tí èékánná rẹ̀ sì dà bí èékánná ẹyẹ.+
-