-
Dáníẹ́lì 4:31-35Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
31 Ọba ò tíì sọ̀rọ̀ yìí tán lẹ́nu tí ohùn kan fi dún láti ọ̀run pé: “À ń sọ fún ìwọ Ọba Nebukadinésárì pé, ‘Ìjọba náà ti kúrò lọ́wọ́ rẹ,+ 32 wọ́n sì máa lé ọ kúrò láàárín àwọn èèyàn. Ọ̀dọ̀ àwọn ẹranko ni wàá máa gbé, a máa fún ọ ní ewéko jẹ bí akọ màlúù, ìgbà méje sì máa kọjá lórí rẹ, títí o fi máa mọ̀ pé Ẹni Gíga Jù Lọ ni Alákòóso nínú ìjọba aráyé, ẹni tó bá sì wù ú ló ń gbé e fún.’”+
33 Ní ìṣẹ́jú yẹn, ọ̀rọ̀ náà ṣẹ sí Nebukadinésárì lára. Wọ́n lé e kúrò láàárín àwọn èèyàn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ ewéko bí akọ màlúù, ìrì ọ̀run sẹ̀ sí i lára, títí irun rẹ̀ fi gùn bí ìyẹ́ idì, tí èékánná rẹ̀ sì dà bí èékánná ẹyẹ.+
34 “Ní òpin àkókò yẹn,+ èmi Nebukadinésárì gbójú sókè ọ̀run, òye mi sì pa dà sínú mi; mo yin Ẹni Gíga Jù Lọ, mo sì fi ìyìn àti ògo fún Ẹni tó wà láàyè títí láé, torí àkóso tó wà títí láé ni àkóso rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.+ 35 Kò ka gbogbo àwọn tó ń gbé ayé sí nǹkan kan, ohun tó bá sì wù ú ló ń ṣe láàárín àwọn ọmọ ogun ọ̀run àti àwọn tó ń gbé ayé. Kò sí ẹni tó lè dá a dúró*+ tàbí kó sọ fún un pé, ‘Kí lo ṣe yìí?’+
-