17 Àṣẹ tí àwọn olùṣọ́+ pa nìyí, àwọn ẹni mímọ́ ló sì béèrè fún un, kí àwọn èèyàn tó wà láàyè lè mọ̀ pé Ẹni Gíga Jù Lọ ni Alákòóso nínú ìjọba aráyé,+ ẹni tó bá wù ú ló ń gbé e fún, ẹni tó sì rẹlẹ̀ jù nínú àwọn èèyàn ló ń fi síbẹ̀.”
27 “‘A sì fún àwọn èèyàn tó jẹ́ ẹni mímọ́ ti Onípò Àjùlọ ní ìjọba, àkóso àti títóbi àwọn ìjọba lábẹ́ gbogbo ọ̀run.+ Ìjọba tó máa wà títí láé ni ìjọba wọn,+ gbogbo ìjọba á máa sìn wọ́n, wọ́n á sì máa ṣègbọràn sí wọn.’