ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 21:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Dúmà:*

      Ẹnì kan ń ké pè mí láti Séírì+ pé:

      “Olùṣọ́, báwo ni òru ṣe rí?

      Olùṣọ́, báwo ni òru ṣe rí?”

  • Ìsíkíẹ́lì 25:12-14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 “Ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí: ‘Édómù ti gbẹ̀san lára ilé Júdà, wọ́n sì ti jẹ̀bi gidigidi torí ẹ̀san tí wọ́n gbà;+ 13 torí náà, ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí: “Màá tún na ọwọ́ mi láti fìyà jẹ Édómù, èmi yóò pa àwọn èèyàn àti ẹran ọ̀sìn ibẹ̀, èmi yóò sì sọ ọ́ di ahoro.+ Idà ni yóò pa wọ́n láti Témánì títí dé Dédánì.+ 14 ‘Màá lo àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì láti gbẹ̀san lára Édómù.+ Wọ́n á mú ìbínú mi àti ìrunú mi wá sórí Édómù, kí wọ́n lè mọ̀ pé èmi ló ń gbẹ̀san lára wọn,’+ ni Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ wí.”’

  • Jóẹ́lì 3:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Àmọ́ Íjíbítì yóò di ahoro,+

      Édómù yóò sì di aginjù tó dá páropáro,+

      Torí bí wọ́n ṣe hùwà ipá sí àwọn ará Júdà,+

      Ilẹ̀ àwọn tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.+

  • Émọ́sì 1:11, 12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Ohun tí Jèhófà sọ nìyí,

      ‘Nítorí ìdìtẹ̀ mẹ́ta Édómù+ àti nítorí mẹ́rin, mi ò ní yí ọwọ́ mi pa dà,

      Nítorí ó fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,+

      Àti nítorí pé ó kọ̀ láti ṣàánú rẹ̀;

      Ó ń fi ìbínú rẹ̀ fà wọ́n ya láìdáwọ́ dúró,

      Kò sì yéé bínú sí wọn.+

      12 Torí náà, màá rán iná sí Témánì,+

      Á sì jó àwọn ilé gogoro tó láàbò ti Bósírà run.’+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́