-
Jeremáyà 27:6, 7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Ní báyìí, mo ti fi gbogbo ilẹ̀ yìí lé ọwọ́ ìránṣẹ́ mi, Nebukadinésárì+ ọba Bábílónì, kódà mo ti fún un ní àwọn ẹran inú igbó kí wọ́n lè máa sìn ín. 7 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò máa sin òun àti ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú ọmọ ọmọ rẹ̀, títí di àkókò tí ìjọba rẹ̀ máa dópin,+ tí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá yóò sì sọ ọ́ di ẹrú wọn.’+
-
-
Sekaráyà 2:7-9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 “Wá, Síónì! Sá àsálà, ìwọ tí ń gbé pẹ̀lú ọmọbìnrin Bábílónì.+ 8 Torí ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí, lẹ́yìn tí a ti yìn ín lógo, ó rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tó ń kó ẹrù yín,+ pé; ‘Ẹni tó bá fọwọ́ kàn yín ń fọwọ́ kan ẹyinjú* mi.+ 9 Wọ́n á rí ìbínú mi, àwọn ìránṣẹ́ wọn yóò sì kó ẹrù wọn.’+ Ó sì dájú pé ẹ máa mọ̀ pé Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ló rán mi.
-