-
Lúùkù 7:18-23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
18 Àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jòhánù wá ròyìn gbogbo nǹkan yìí fún un.+ 19 Torí náà, Jòhánù pe méjì nínú àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì rán wọn sí Olúwa pé kí wọ́n bi í pé: “Ṣé ìwọ ni Ẹni Tó Ń Bọ̀,+ àbí ká máa retí ẹlòmíì?” 20 Nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọkùnrin náà sọ pé: “Jòhánù Arinibọmi rán wa sí ọ láti béèrè pé, ‘Ṣé ìwọ ni Ẹni Tó Ń Bọ̀, àbí ká máa retí ẹlòmíì?’” 21 Ní wákàtí yẹn, ó ṣe ìwòsàn fún ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn,+ àwọn tó ní àrùn tó le àti àwọn tó ní ẹ̀mí burúkú, ó sì mú kí ọ̀pọ̀ afọ́jú pa dà ríran. 22 Ó dá wọn lóhùn pé: “Ẹ lọ ròyìn ohun tí ẹ ti rí, tí ẹ sì ti gbọ́ fún Jòhánù: Àwọn afọ́jú ti ń ríran báyìí,+ àwọn arọ ń rìn, à ń wẹ àwọn adẹ́tẹ̀ mọ́, àwọn adití ń gbọ́ràn,+ à ń jí àwọn òkú dìde, a sì ń sọ ìhìn rere fún àwọn aláìní.+ 23 Aláyọ̀ ni ẹni tí kò rí ohunkóhun tó máa mú kó kọsẹ̀ nínú mi.”+
-