-
Lúùkù 7:31-35Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
31 “Ta ni màá wá fi àwọn èèyàn ìran yìí wé, ta ni wọ́n sì jọ?+ 32 Wọ́n dà bí àwọn ọmọ kéékèèké tí wọ́n jókòó nínú ọjà, tí wọ́n sì ń ké pe ara wọn, tí wọ́n ń sọ pé: ‘A fun fèrè fún yín, àmọ́ ẹ ò jó; a pohùn réré ẹkún, àmọ́ ẹ ò sunkún.’ 33 Bákan náà, Jòhánù Arinibọmi wá, kò jẹ búrẹ́dì, kò sì mu wáìnì,+ àmọ́ ẹ sọ pé, ‘Ẹlẹ́mìí èṣù ni.’ 34 Ọmọ èèyàn wá, ó ń jẹ, ó sì ń mu, àmọ́ ẹ sọ pé: ‘Wò ó! Ọkùnrin alájẹkì, ti kò mọ̀ ju kó mu wáìnì lọ, ọ̀rẹ́ àwọn agbowó orí àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀!’+ 35 Síbẹ̀ náà, a fi ọgbọ́n hàn ní olódodo* nípasẹ̀ gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀.”*+
-