-
Mátíù 21:23-27Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 Lẹ́yìn tó lọ sínú tẹ́ńpìlì, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbààgbà àwọn èèyàn náà wá sọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tó ń kọ́ni, wọ́n sì sọ pé: “Àṣẹ wo lo fi ń ṣe àwọn nǹkan yìí? Ta ló sì fún ọ ní àṣẹ yìí?”+ 24 Jésù dá wọn lóhùn pé: “Èmi náà á bi yín ní ohun kan, tí ẹ bá sọ fún mi, èmi náà á sọ àṣẹ tí mo fi ń ṣe àwọn nǹkan yìí fún yín: 25 Ìrìbọmi tí Jòhánù ṣe fún àwọn èèyàn, ibo ló ti wá? Ṣé láti ọ̀run ni àbí látọ̀dọ̀ èèyàn?”* Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í rò ó láàárín ara wọn pé: “Tí a bá sọ pé, ‘Láti ọ̀run,’ ó máa sọ fún wa pé, ‘Kí ló wá dé tí ẹ ò gbà á+ gbọ́?’ 26 Àmọ́ tí a bá sọ pé, ‘Látọ̀dọ̀ èèyàn,’ ẹ̀rù àwọn èrò yìí ń bà wá, torí wòlíì ni gbogbo wọn ka Jòhánù sí.” 27 Torí náà, wọ́n dá Jésù lóhùn pé: “A ò mọ̀.” Ó wá sọ fún wọn pé: “Èmi náà ò ní sọ àṣẹ tí mo fi ń ṣe àwọn nǹkan yìí fún yín.
-
-
Lúùkù 20:1-8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
20 Lọ́jọ́ kan, bó ṣe ń kọ́ àwọn èèyàn nínú tẹ́ńpìlì, tó sì ń kéde ìhìn rere, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé òfin pẹ̀lú àwọn àgbààgbà wá, 2 wọ́n sì bi í pé: “Sọ fún wa, àṣẹ wo lo fi ń ṣe àwọn nǹkan yìí? Àbí ta ló fún ọ ní àṣẹ yìí?”+ 3 Ó dá wọn lóhùn pé: “Èmi náà á bi yín ní ìbéèrè kan, kí ẹ sì dá mi lóhùn: 4 Ṣé láti ọ̀run ni ìrìbọmi tí Jòhánù ṣe fún àwọn èèyàn ti wá àbí látọ̀dọ̀ èèyàn?” 5 Wọ́n jọ rò ó láàárín ara wọn, wọ́n ní: “Tí a bá sọ pé, ‘Láti ọ̀run,’ ó máa sọ pé, ‘Kí ló dé tí ẹ ò gbà á gbọ́?’ 6 Àmọ́ tí a bá sọ pé, ‘Látọ̀dọ̀ èèyàn,’ gbogbo èèyàn ló máa sọ wá lókùúta, torí ó dá wọn lójú pé wòlíì ni Jòhánù.”+ 7 Nítorí náà, wọ́n fèsì pé àwọn ò mọ orísun rẹ̀. 8 Jésù wá sọ fún wọn pé: “Èmi náà ò ní sọ àṣẹ tí mo fi ń ṣe àwọn nǹkan yìí fún yín.”
-