-
Mátíù 9:16, 17Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
16 Kò sí ẹni tó máa rán ègé aṣọ tí kò tíì sún kì mọ́ ara aṣọ àwọ̀lékè tó ti gbó, torí aṣọ tuntun náà máa ya kúrò lára aṣọ àwọ̀lékè náà, ó sì máa ya ju ti tẹ́lẹ̀ lọ.+ 17 Àwọn èèyàn kì í sì í rọ wáìnì tuntun sínú àpò awọ tó ti gbó. Tí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, àpò náà máa bẹ́, wáìnì á dà nù, àpò náà á sì bà jẹ́. Àmọ́ inú àpò awọ tuntun ni àwọn èèyàn máa ń rọ wáìnì tuntun sí, ohunkóhun ò sì ní ṣe méjèèjì.”
-
-
Máàkù 2:21, 22Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 Kò sí ẹni tó máa rán ègé aṣọ tí kò tíì sún kì mọ́ ara aṣọ àwọ̀lékè tó ti gbó. Tó bá ṣe bẹ́ẹ̀, aṣọ tuntun náà máa ya kúrò lára èyí tó ti gbó, ó sì máa ya ju ti tẹ́lẹ̀ lọ.+ 22 Bákan náà, kò sí ẹni tó máa rọ wáìnì tuntun sínú àpò awọ tó ti gbó. Tó bá ṣe bẹ́ẹ̀, wáìnì tuntun máa bẹ́ awọ náà, wáìnì náà máa dà nù, awọ náà sì máa bà jẹ́. Àmọ́ inú àpò awọ tuntun ni wọ́n máa ń rọ wáìnì tuntun sí.”
-