9 Àmọ́ Sọ́ọ̀lù, tí inú rẹ̀ ṣì ń ru, tó sì ń fikú halẹ̀ mọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn Olúwa,+ lọ bá àlùfáà àgbà, 2 ó sì ní kí ó fún òun ní àwọn lẹ́tà sí àwọn sínágọ́gù ní Damásíkù, kí ó lè mú ẹnikẹ́ni tó bá rí tí ó jẹ́ ti Ọ̀nà Náà+ wá sí Jerúsálẹ́mù ní dídè, àti ọkùnrin àti obìnrin.