30 Torí náà, ó lo odindi ọdún méjì ní ilé tí òun fúnra rẹ̀ gbà,+ ó sì máa ń gba gbogbo àwọn tó bá wá sọ́dọ̀ rẹ̀ tọwọ́tẹsẹ̀, 31 ó ń wàásù Ìjọba Ọlọ́run fún wọn, ó sì ń kọ́ wọn nípa Jésù Kristi Olúwa ní fàlàlà,*+ láìsí ìdíwọ́.
23 kìkì pé kí ẹ dúró nínú ìgbàgbọ́,+ kí ẹ fìdí múlẹ̀ lórí ìpìlẹ̀ náà,+ kí ẹ sì fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin,+ kí ẹ má yà kúrò nínú ìrètí ìhìn rere tí ẹ gbọ́, tí a sì ti wàásù láàárín gbogbo ẹ̀dá tó wà lábẹ́ ọ̀run.+ Torí ìhìn rere yìí la ṣe yan èmi Pọ́ọ̀lù láti di òjíṣẹ́.+