-
Ẹ́kísódù 12:21-23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 Mósè yára pe gbogbo àgbààgbà Ísírẹ́lì,+ ó sì sọ fún wọn pé: “Ẹ lọ mú àwọn ọmọ ẹran* fún ìdílé yín níkọ̀ọ̀kan, kí ẹ sì pa ẹran tí ẹ máa fi rúbọ nígbà Ìrékọjá. 22 Kí ẹ wá ki ìdìpọ̀ ewéko hísópù bọnú ẹ̀jẹ̀ tó wà nínú bàsíà, kí ẹ sì wọ́n ọn sí apá òkè ẹnu ọ̀nà àti sára òpó méjèèjì ilẹ̀kùn náà; kí ẹnì kankan nínú yín má sì jáde ní ẹnu ọ̀nà ilé rẹ̀ títí di àárọ̀. 23 Tí Jèhófà bá wá kọjá kó lè fi ìyọnu kọ lu àwọn ará Íjíbítì, tó sì rí ẹ̀jẹ̀ náà ní apá òkè ẹnu ọ̀nà àti lára òpó rẹ̀ méjèèjì, ó dájú pé Jèhófà yóò ré ẹnu ọ̀nà náà kọjá, kò sì ní jẹ́ kí ìyọnu ikú* wọnú ilé yín.+
-