ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • jy orí 118 ojú ìwé 272-ojú ìwé 273 ìpínrọ̀ 1
  • Wọ́n Jiyàn Nípa Ẹni Tó Tóbi Jù

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Wọ́n Jiyàn Nípa Ẹni Tó Tóbi Jù
  • Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìjiyàn kan Bẹ Silẹ
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • “Jésù . . . Nífẹ̀ẹ́ Wọn Dé Òpin”
    “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
  • Mimura Awọn Apọsiteli Silẹ fun Igberalọ Rẹ̀
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • Kí ni Jèhófà Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa Lónìí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
Àwọn Míì
Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
jy orí 118 ojú ìwé 272-ojú ìwé 273 ìpínrọ̀ 1
Àwọn àpọ́sítélì ń jiyàn nípa ẹni tó tóbi jù láàárín wọn

ORÍ 118

Wọ́n Jiyàn Nípa Ẹni Tó Tóbi Jù

Mátíù 26:31-35 Máàkù 14:27-31 Lúùkù 22:24-38 Jòhánù 13:31-38

  • JÉSÙ FÚN ÀWỌN ỌMỌ Ẹ̀YÌN RẸ̀ NÍMỌ̀RÀN PÉ KÍ WỌ́N MÁ ṢE MÁA WÁ IPÒ ỌLÁ

  • JÉSÙ SỌ TẸ́LẸ̀ PÉ PÉTÉRÙ MÁA SẸ́ ÒUN

  • ÌFẸ́ NI WỌ́N Á FI DÁ ÀWỌN ỌMỌ Ẹ̀YÌN JÉSÙ MỌ̀

Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí Jésù lò kẹ́yìn pẹ̀lú àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀, ó kọ́ wọn ní ẹ̀kọ́ pàtàkì kan nípa ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ nígbà tó fọ ẹsẹ̀ wọn. Ohun tó sọ yẹn bọ́ sákòókò gan-an ni. Kí nìdí? Ìdí ni pé ó yẹ kí wọ́n kọ́ bí wọ́n ṣe máa ní ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀. Wọ́n nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run lóòótọ́, àmọ́ ọ̀rọ̀ nípa ẹni tó tóbi jù láàárín wọn ṣì ń jẹ wọ́n lọ́kàn. (Máàkù 9:33, 34; 10:35-37) Ọ̀rọ̀ yẹn tún fa wàhálà láàárín wọn nírọ̀lẹ́ ọjọ́ yẹn.

Àwọn àpọ́sítélì náà “bẹ̀rẹ̀ sí í bára wọn jiyàn gidigidi nípa ẹni tí wọ́n kà sí ẹni tó tóbi jù nínú wọn.” (Lúùkù 22:24) Ẹ wo bí ẹ̀dùn ọkàn ṣe máa bá Jésù nígbà tó rí i tí wọ́n ń bá ara wọn jiyàn láìnídìí! Kí ni Jésù wá ṣe?

Dípò kí Jésù láálí wọn, ṣe ló fi sùúrù bá wọn sọ̀rọ̀, ó ní: “Àwọn ọba àwọn orílẹ̀-èdè máa ń jẹ ọ̀gá lé àwọn èèyàn lórí, wọ́n sì máa ń pe àwọn tó ní àṣẹ lórí wọn ní Olóore. Àmọ́ kò yẹ kí ẹ̀yin ṣe bẹ́ẹ̀. . . . Torí ta ló tóbi jù, ṣé ẹni tó ń jẹun ni àbí ẹni tó ń gbé oúnjẹ wá?” Jésù wá rán wọn létí àwọn àpẹẹrẹ àtàtà tó ti fi lẹ́lẹ̀ fún wọn, ó ní: “Àmọ́ mo wà láàárín yín bí ẹni tó ń gbé oúnjẹ wá.”—Lúùkù 22:25-27.

Láìka pé àwọn àpọ́sítélì yìí jẹ́ aláìpé, wọ́n dúró ti Jésù gbágbáágbá nígbà ìṣòro. Torí náà, Jésù sọ pé: “Mo . . . bá yín dá májẹ̀mú fún ìjọba kan, bí Baba mi ṣe bá mi dá májẹ̀mú.” (Lúùkù 22:29) Gbogbo ọkàn làwọn ọkùnrin yìí fi ń tẹ̀ lé Jésù. Torí náà, Jésù fi dá wọn lójú pé òun máa dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú wọn, kó lè ṣeé ṣe fún wọn láti wà nínú Ìjọba rẹ̀, kí wọ́n sì bá a jọba.

Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn àpọ́sítélì nírú ìrètí yìí, áláìpé ṣì ni wọ́n. Jésù wá sọ fún wọn pé: “Sátánì ti béèrè pé òun fẹ́ gba gbogbo yín, kó lè kù yín bí àlìkámà,” tó máa ń fọ́n ká tí wọ́n bá kù ú. (Lúùkù 22:31) Ó tún kìlọ̀ fún wọn pé: “Gbogbo yín lẹ máa kọsẹ̀ torí ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí mi lóru òní, torí a ti kọ ọ́ pé: ‘Màá kọ lu olùṣọ́ àgùntàn, àwọn àgùntàn inú agbo sì máa tú ká.’ ”—Mátíù 26:31; Sekaráyà 13:7.

Gbogbo ẹnu ni Pétérù fi sọ pé: “Tí gbogbo àwọn yòókù bá tiẹ̀ kọsẹ̀ torí ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí ọ, ó dájú pé èmi ò ní kọsẹ̀ láé!” (Mátíù 26:33) Jésù wá sọ fún Pétérù pé ó máa sẹ́ òun kí àkùkọ tó kọ lẹ́ẹ̀mejì lálẹ́ ọjọ́ yẹn. Àmọ́ Jésù sọ pé: “Mo ti bá yín bẹ̀bẹ̀, kí ìgbàgbọ́ yín má bàa yẹ̀; ní ti ìwọ, gbàrà tí o bá pa dà, fún àwọn arákùnrin rẹ lókun.” (Lúùkù 22:32) Síbẹ̀ Pétérù fi ìdánilójú sọ fún Jésù pé: “Àní tó bá tiẹ̀ gba pé kí n kú pẹ̀lú rẹ pàápàá, ó dájú pé mi ò ní sẹ́ ọ.” (Mátíù 26:35) Àwọn tó kù sì sọ ohun kan náà.

Jésù sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Ìgbà díẹ̀ sí i ni màá fi wà pẹ̀lú yín. Ẹ máa wá mi; bí mo sì ṣe sọ fún àwọn Júù pé, ‘Ẹ ò lè wá sí ibi tí mò ń lọ,’ mò ń sọ fún ẹ̀yin náà báyìí.” Ó wá fi kún un pé: “Mò ń fún yín ní àṣẹ tuntun kan, pé kí ẹ nífẹ̀ẹ́ ara yín; bí mo ṣe nífẹ̀ẹ́ yín, kí ẹ̀yin náà nífẹ̀ẹ́ ara yín. Èyí ni gbogbo èèyàn máa fi mọ̀ pé ọmọ ẹ̀yìn mi ni yín, tí ìfẹ́ bá wà láàárín yín.”—Jòhánù 13:33-35.

Bí Pétérù ṣe gbọ́ tí Jésù sọ pé òun ò ní pẹ́ lọ, ó béèrè pé: “Olúwa, ibo lò ń lọ?” Jésù dáhùn pé: “O ò lè tẹ̀ lé mi lọ síbi tí mò ń lọ báyìí, àmọ́ o máa tẹ̀ lé mi tó bá yá.” Pétérù sọ fún un pé: “Olúwa, kí ló dé tí mi ò lè tẹ̀ lé ọ báyìí? Màá fi ẹ̀mí mi lélẹ̀ nítorí rẹ.”—Jòhánù 13:36, 37.

Jésù rán wọn létí ìgbà tó rán wọn lọ sí agbègbè Gálílì láti lọ wàásù, tó sì ní kí wọ́n má ṣe mú àmùrè tí wọ́n ń kó owó sí tàbí àpò oúnjẹ dání. (Mátíù 10:5, 9, 10) Ó wá bi wọ́n pé: “Ẹ ò ṣaláìní nǹkan kan, àbí ẹ ṣaláìní?” Wọ́n dá a lóhùn pé: “Rárá!” Àmọ́, ṣé bí wọ́n á ṣe máa ṣe lọ nìyẹn? Jésù fún wọn ní ìtọ́ni míì, ó ní: “Kí ẹni tó ní àpò owó gbé e, bẹ́ẹ̀ náà ni àpò oúnjẹ, kí ẹni tí kò bá ní idà ta aṣọ àwọ̀lékè rẹ̀, kó sì ra ọ̀kan. Torí mò ń sọ fún yín pé ohun tó wà ní àkọsílẹ̀ ni wọ́n gbọ́dọ̀ ṣe sí mi délẹ̀délẹ̀, pé, ‘A kà á mọ́ àwọn arúfin.’ Torí èyí ń ṣẹ sí mi lára.”—Lúùkù 22:35-37.

Nígbà tí Jésù sọ̀rọ̀ yìí, ó ń tọ́ka sí bí wọ́n ṣe máa kan òun mọ́gi pẹ̀lú àwọn èèyàn burúkú tàbí àwọn arúfin. Lẹ́yìn ìyẹn, àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ máa kojú inúnibíni tó lágbára. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn yẹn rò pé àwọn ti ṣe tán láti kojú inúnibíni èyíkéyìí, wọ́n wá sọ pé: “Olúwa, wò ó! idà méjì nìyí.” Jésù wá dá wọn lóhùn pé: “Ó ti tó.” (Lúùkù 22:38) Bí wọ́n ṣe ní idà méjì yẹn máa jẹ́ kí Jésù lè kọ́ wọn ní ẹ̀kọ́ pàtàkì kan láìpẹ́ sígbà yẹn.

  • Kí làwọn àpọ́sítélì ń jiyàn lé lórí, báwo sì ni Jésù ṣe yanjú ẹ̀?

  • Àǹfààní wo ni àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù tó jẹ́ olóòótọ́ máa rí nínú májẹ̀mú tí Jésù bá wọn dá?

  • Kí ni Jésù sọ nígbà tí Pétérù fi ìdánilójú dá a lóhùn?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́