ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 78 ojú ìwé 184-ojú ìwé 185 ìpínrọ̀ 1
  • Jésù Wàásù Nípa Ìjọba Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jésù Wàásù Nípa Ìjọba Ọlọ́run
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Ẹ Lọ, Kí Ẹ sì Máa Sọ Àwọn Ènìyàn . . . Di Ọmọ Ẹ̀yìn”
    “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
  • Jésù Rán Àádọ́rin (70) Ọmọ Ẹ̀yìn Jáde Lọ Wàásù
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Jésù Mú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ̀ Gbòòrò Sí I ní Gálílì
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Ìdí Ti Jesu Fi Wá sí Aye
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 78 ojú ìwé 184-ojú ìwé 185 ìpínrọ̀ 1
Jésù àti ọmọ ẹ̀yìn kan ń wàásù

Ẹ̀KỌ́ 78

Jésù Wàásù Nípa Ìjọba Ọlọ́run

Kò pẹ́ tí Jésù ṣèrìbọmi ló bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù pé: ‘Ìjọba Ọlọ́run ti sún mọ́lé.’ Àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ ń tẹ̀ lé e bó ṣe ń wàásù nílùú Gálílì àti Jùdíà. Nígbà tó pa dà sílùú Násárẹ́tì tí wọ́n bí i sí, ó lọ sínú sínágọ́gù, ó ṣí àkájọ ìwé Àìsáyà, ó sì kà á sókè. Ó ní: ‘Jèhófà ti fún mi ní ẹ̀mí mímọ́ kí n lè wàásù ìhìn rere fáwọn èèyàn.’ Àmọ́, kí nìyẹn túmọ̀ sí? Ohun tó túmọ̀ sí ni pé bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn èèyàn fẹ́ kí Jésù máa ṣe iṣẹ́ ìyanu, ìdí tí Jèhófà fi fún un ní ẹ̀mí mímọ́ ni pé kó lè máa wàásù ìhìn rere. Ó wá sọ fáwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀ pé: ‘Lónìí, àsọtẹ́lẹ̀ yìí ṣẹ.’

Lẹ́yìn ìyẹn, Jésù lọ sí Òkun Gálílì, ibẹ̀ ló ti rí mẹ́rin lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ tí wọ́n jẹ́ apẹja. Ó sọ fún wọn pé: ‘Ẹ tẹ̀ lé mi, màá sọ yín di apẹja èèyàn.’ Orúkọ àwọn mẹ́rin náà ni Pétérù, Áńdérù, Jémíìsì àti Jòhánù. Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ tí Jésù pè wọ́n ni wọ́n fi iṣẹ́ ẹja pípa sílẹ̀, tí wọ́n sì tẹ̀ lé e. Wọ́n ń wàásù nípa Ìjọba Jèhófà ní gbogbo ìlú Gálílì. Wọ́n wàásù nínú sínágọ́gù, nínú ọjà àti lójú ọ̀nà. Àmọ́ gbogbo ibi tí wọ́n ń lọ ni èrò ti ń tẹ̀ lé wọn. Ibi gbogbo làwọn èèyàn ti gbọ́ nípa Jésù, kódà wọ́n gbọ́ nípa ẹ̀ nílùú Síríà.

Nígbà tó yá, Jésù fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn kan ní agbára láti wo àwọn èèyàn sàn kí wọ́n sì lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde. Àwọn míì sì wà pẹ̀lú ẹ̀ bó ṣe ń wàásù láti ìlú kan sí ìlú míì àti láti abúlé kan sí òmíì. Àwọn obìnrin olóòótọ́ kan máa ń ran Jésù àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ lọ́wọ́. Lára wọn ni Màríà Magidalénì, Jòánà, Súsánà àtàwọn míì.

Lẹ́yìn tí Jésù kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ dáadáa, ó rán wọn jáde láti lọ wàásù. Bí wọ́n ṣe ń wàásù ní gbogbo ìlú Gálílì, ọ̀pọ̀ èèyàn di ọmọ ẹ̀yìn wọ́n sì ṣèrìbọmi. Àwọn tó fẹ́ di ọmọ ẹ̀yìn pọ̀ débi pé Jésù fi wọ́n wé àwọn èso tó ti pọ́n tó yẹ kí wọ́n ká. Ó wá sọ pé: ‘Ẹ gbàdúrà sí Jèhófà pé kó rán àwọn òṣìṣẹ́ jáde kí wọ́n lè kórè oko náà.’ Nígbà tó yá, ó yan àádọ́rin (70) lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀, ó sì rán wọn jáde ní méjì-méjì kí wọ́n lè wàásù ní gbogbo agbègbè Jùdíà. Wọ́n ń wàásù nípa Ìjọba Ọlọ́run fún gbogbo èèyàn. Nígbà tí wọ́n pa dà dé, inú wọn dùn láti sọ gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ fún Jésù. Ẹ ò rí i pé kò sóhun tí Èṣù lè ṣe láti dá iṣẹ́ ìwàásù náà dúró.

Jésù rí i dájú pé òun kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn òun dáadáa kí wọ́n lè máa bá iṣẹ́ ìwàásù náà lọ lẹ́yìn tí òun bá pa dà sí ọ̀run. Ó sọ fún wọn pé: ‘Ẹ wàásù ìhìn rere náà kárí ayé. Ẹ máa kọ́ àwọn èèyàn ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kẹ́ ẹ sì máa batisí wọn.’

“Mo tún gbọ́dọ̀ kéde ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú míì, torí pé nítorí èyí la ṣe rán mi.”​—Lúùkù 4:43

Ìbéèrè: Iṣẹ́ wo ni Jésù gbé fáwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀? Báwo ni iṣẹ́ tí Jésù gbé fáwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ ṣe rí lára wọn?

Mátíù 4:17-25; 9:35-38; 28:19, 20; Máàkù 1:14-20; Lúùkù 4:14-21; 8:1-3; 10:1-22

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́