ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w92 12/15 ojú ìwé 32
  • Sisọ Asọtẹlẹ Ọjọ-ọla Eto Ọrọ̀-ajé Àgbáyé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Sisọ Asọtẹlẹ Ọjọ-ọla Eto Ọrọ̀-ajé Àgbáyé
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
w92 12/15 ojú ìwé 32

Sisọ Asọtẹlẹ Ọjọ-ọla Eto Ọrọ̀-ajé Àgbáyé

AIDURO deedee ọjà eto ọrọ̀-ajé ati ainigbọkanle ninu awọn oluṣayẹwo kulẹkulẹ ti wọn kuna lati sọ asọtẹlẹ iwolulẹ ọjà eto ìdókòwò ní 1987 ti mu ki awọn oniṣowo melookan yiju si iworawọ-sọtẹlẹ lati sọ asọtẹlẹ ọjọ-ọla eto owó wọn, ni iwe-irohin London naa Accountancy Age sọ. Iwe-irohin naa sọ pe “awọn aworawọ-sọtẹlẹ eto owó ti ń jere akọsilẹ ẹgbẹ́ awọn oníbàárà onípò-iyì pupọ gan-an fun asọtẹlẹ wọn lori kulẹkulẹ ipa-ọna igbokegbodo òwò.”

Ẹnikan ti a kàn sí fi awọn iyipo ti oun ti ri ni 30 ọdun akọsilẹ eto owó ojoojumọ wéra pẹlu iṣipopada awọn planeti. Lori ipilẹ yii o funni ní asọtẹlẹ rẹ̀. Bi o tilẹ jẹ pe ọpọ awọn oníbàárà ń lọ́tìkọ̀ lati kọbiara si amọran rẹ̀ ṣaaju 1987, nisinsinyi oun ri koda awọn olorikunkun eleto owó ti wọn muratan lati fetisilẹ.

Aworawo-sọtẹlẹ eto owó miiran ya aworan ti a gbekari awọn ọjọ ìbí lati díwọ̀n animọ ẹnikan ati lati ṣawari “ọ̀nà ojútùú si akoko ti idagbasoke iṣowo yoo ṣeeṣe” pẹlu. Sibẹ òmíràn gbagbọ pe iyipada leralera ọjà fàdákà ń tẹ̀lé iyipo oṣupa. Ṣugbọn nigba ti a bá fiwera pẹlu awọn oluṣayẹwo kulẹkulẹ eto owó ti o wọpọ, aworawọ-sọtẹlẹ yii rii pe awọn oníbàárà rẹ̀ fun un “ní ààyè ti o kere gidigidi fun ṣíṣìnà.”

Bi o ti wu ki o ri, asọtẹlẹ kan wà lori eto owó ti o daju pe yoo jẹ́ otitọ, kò si ní ohunkohun ṣe pẹlu iworawọsọtẹlẹ. Asọtẹlẹ yii ni a kọsilẹ ninu Bibeli ti Jehofa sì mísí, Ọlọrun naa ti kò fun araarẹ̀ ní “ààyè fun ṣíṣìnà” rara. O jẹ Ọlọrun ti “kò lè ṣeke.” (Titu 1:2) O mu ki wolii rẹ̀ Esekieli polongo pe: “Wọn o sọ fadaka wọn si igboro, wura wọn ni a o si mu kuro; fadaka wọn ati wura wọn kì yoo si lè gbà wọn là ni ọjọ ibinu Oluwa.”—Esekiel 7:19.

Nigba wo ni eyi yoo jẹ́? Nigba “ipọnju nla” ti ń bọ̀ ti Jesu Kristi sọtẹlẹ, eyi ti Esekieli pè ní “ọjọ ibinu Oluwa.” (Matteu 24:21; Esekiel 7:19) Aásìkí eto owó kìí yoo mu lilaaja daju, laika ohun ti awọn aworawọ-sọtẹlẹ lè sọtẹlẹ si. Kiki igbọnkale ninu Jehofa Ọlọrun, Oludande Nla naa, ni o lè mu ailewu daju nigba irugudu yika ayé yii ninu eyi ti a o ti mu gbogbo iwa ibajẹ kuro—ti oṣelu, isin, ati ti iṣowo.—Owe 3:5, 6; Sefaniah 2:3; 2 Peteru 2:9.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́