ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w96 4/1 ojú ìwé 31
  • Ìgbàgbọ́ Sún un Láti Gbégbèésẹ̀

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìgbàgbọ́ Sún un Láti Gbégbèésẹ̀
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
w96 4/1 ojú ìwé 31

Ìgbàgbọ́ Sún un Láti Gbégbèésẹ̀

NÍGBÀ tí Jehofa pàṣẹ fún Mose láti ṣáájú orílẹ̀-èdè Israeli kúrò nínú oko ẹrú àwọn ará Egipti, lákọ̀ọ́kọ́, Mose bẹ̀bẹ̀ pé kí a yọ̀ọ̀da òun, ní sísọ pé: “Oluwa, èmi kì í ṣe ẹni ọ̀rọ̀ sísọ nígbà àtijọ́ wá, tàbí láti ìgbà tí o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀: ṣùgbọ́n olóhùn wúwo ni mí, àti aláhọ́n wúwo.” (Eksodu 4:10) Bẹ́ẹ̀ ni, Mose nímọ̀lára àìtóótun fún irú iṣẹ́ àyànfúnni bàǹtàbanta bẹ́ẹ̀.

Bákan náà lónìí, nígbà míràn, ọ̀pọ̀ ìránṣẹ́ Jehofa máa ń nímọ̀lára àìtóótun láti ṣe iṣẹ́ tí a yàn fún wọn. Fún àpẹẹrẹ, Kristian alábòójútó kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Theodore ròyìn pé: “Nínú gbogbo ohun tí Jehofa ní kí n ṣe, iṣẹ́ ìsìn pápá ni ó le jù. Nígbà tí mo wà ní kékeré, n óò sáré rìn lọ sí ẹnu ọ̀nà, n óò díbọ́n bíi pé mo kan ilẹ̀kùn, n óò sì rìn kánmọ́kánmọ́ kúrò níbẹ̀, pẹ̀lú ìrètí pé ẹni kẹ́ni kò gbọ́ tàbí rí mi. Bí mo ti ń dàgbà, mo dẹ́kun ṣíṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n èrò àti lọ láti ilé dé ilé máa ń mú mi ṣàárẹ̀. Àní títí di ìsinsìnyí pàápàá, ojora máa ń mù mi ṣáájú jíjáde lọ fún iṣẹ́ òjíṣẹ́, ṣùgbọ́n mo ṣì máa ń lọ.”

Kí ni ó mú kí Mose àti àwọn Ẹlẹ́rìí òde òní bíi Theodore lè kápá irú ìbẹ̀rù bẹ́ẹ̀? Bibeli dáhùn pé: “Nipa ìgbàgbọ́ ni ó [Mose] fi Egipti sílẹ̀, . . . nitori tí ó ń bá a lọ ní fífẹsẹ̀múlẹ̀ ṣinṣin bí ẹni tí ń rí Ẹni naa tí a kò lè rí.”—Heberu 11:27.

Ní tòótọ́, nípa lílo ìgbàgbọ́ nínú Jehofa, ó ṣeé ṣe fún Mose láti borí ìmọ̀lára àìtóótun rẹ̀, kí ó sì ṣe iṣẹ́ tí a yàn fún un gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́, wòlíì, aṣáájú orílẹ̀-èdè, alárinà májẹ̀mú Òfin, aláṣẹ, òpìtàn, àti akọ̀wé Bibeli.

Bákan náà, nígbà tí a bá ní ìgbàgbọ́ bíi Mose, a óò rìn bí ẹni tí ‘ń rí Ẹni náà tí a kò lè rí.’ Irú ìgbàgbọ́ bẹ́ẹ̀ ń gbé ìgboyà ró, ní ríràn wá lọ́wọ́ láti gbé àwọn ẹrù iṣẹ́ Kristian wa—àní nígbà tí a bá nímọ̀lára àìtóótun pàápàá.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́