ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w00 4/15 ojú ìwé 32
  • Ẹ̀bùn Tó Ṣeyebíye Lójú Jèhófà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹ̀bùn Tó Ṣeyebíye Lójú Jèhófà
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
w00 4/15 ojú ìwé 32

Ẹ̀bùn Tó Ṣeyebíye Lójú Jèhófà

Ẹ̀ka iléeṣẹ́ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní Mòsáńbíìkì rí lẹ́tà tó tẹ̀ le yìí gbà:

“Ọmọdékùnrin ọlọ́dún méje ni mí. Ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ni mo ṣì wà. Mò ń fi owó yìí tí mo rí nígbà tí mo ta àkùkọ mi tí mò ń sìn ránṣẹ́. Ẹgbẹ̀rún méjìlá Métíkà owó ilẹ̀ Mòsáńbíìkì [dọ́là kan owó ilẹ̀ Amẹ́ríkà] ni mo tà á. Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà tó jẹ́ kí ọmọ adìẹ tí màá kọ́kọ́ sìn láyé mi dàgbà di àkùkọ ńlá. Màá fẹ́ ká lo ẹ̀bùn mi fún iṣẹ́ Ìjọba Jèhófà.

“Àfikún àlàyé: Baba mi ló bá mi kọ̀wé yìí.”

Lójú àwọn kan, kìkì àwọn tó jẹ ṣẹ́ kù nìkan ló lè lẹ́mìí ọ̀làwọ́. Bí ó ti wù kí ó rí, nígbà táa bá ka àkọsílẹ̀ Bíbélì nípa opó tó sọ “ẹyọ owó kéékèèké méjì tí ìníyelórí wọn kéré gan-an” sínú àpótí ìṣúra, a lè wá mọyì ẹ̀ pé kìí ṣe bí nǹkan ṣe pọ̀ tó la fi ń sọ pé èèyàn lẹ́mìí ọ̀làwọ́, bí kò ṣe kéèyàn nítẹ̀sí ọkàn-àyà tó tọ́.—Lúùkù 21:1-4.

Bó ti wù kẹ́bùn kan ó kéré tó, Jèhófà máa ń mọrírì rẹ̀, tó bá ti tinú ọkàn tí ìfẹ́ sún ṣiṣẹ́ wá. Wọ̀ǹtì-wọnti ló sì máa ń bù kún àwọn tó bá ṣàfarawé ẹ̀mí ọ̀làwọ́ rẹ̀ nípa lílo àkókò, okun, tàbí ohun ìní wọn nípa tara nítorí Ìjọba rẹ̀.—Mátíù 6:33; Hébérù 6:10.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́