ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w02 11/1 ojú ìwé 32
  • Gbogbo Wa La Máa Ń Fẹ́ Ká Gbóríyìn fún Wa

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Gbogbo Wa La Máa Ń Fẹ́ Ká Gbóríyìn fún Wa
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
w02 11/1 ojú ìwé 32

Gbogbo Wa La Máa Ń Fẹ́ Ká Gbóríyìn fún Wa

ỌJỌ́ tó dáa gan-an ni ọjọ́ yẹn jẹ́ fún ọmọbìnrin kékeré náà. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó máa ń ṣe àwọn nǹkan tí wọ́n fi máa ń bá a wí láwọn ìgbà mìíràn, àmọ́ ó dìídì hùwà ọmọlúàbí lọ́jọ́ tá à ń wí yìí. Ṣùgbọ́n nígbà tó di alẹ́ ọjọ́ náà, lẹ́yìn tí wọ́n tẹ́ ọmọdébìnrin náà sórí ibùsùn, ìyá rẹ gbọ́ ẹkún rẹ̀. Nígbà tó béèrè ohun tó ń pa á nígbe, pẹ̀lú omijé lójú ló fi sọ pé: “Ṣé mi ò ṣe dáadáa lónìí ni?”

Ìbéèrè yẹn ba ìyá rẹ̀ nínú jẹ́ gan-an ni. Gbogbo ìgbà ló máa ń yára bá ọmọ rẹ̀ wí nígbà tó bá ṣe àṣìṣe. Àmọ́ lọ́jọ́ tá à ń wí yìí, pẹ̀lú gbogbo bí ìyá yìí ṣe kíyè sí i pé ọmọdébìnrin òun sá gbogbo ipá rẹ̀ láti hùwà ọmọlúàbí tó, kò tiẹ̀ sọ ọ̀rọ̀ kan láti fi hàn pé òun mọrírì ohun tí ọmọ náà ṣe.

Kì í ṣe àwọn ọmọdé nìkan ló fẹ́ ká gbóríyìn fáwọn ká sì fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀. Gbogbo wa la fẹ́ bẹ́ẹ̀—gẹ́gẹ́ bá a ṣe fẹ́ ìmọ̀ràn àti ìbáwí.

Báwo ló ṣe máa ń rí lára wa nígbà tí wọ́n bá gbóríyìn fún wa látọkànwá? Ǹjẹ́ kì í múnú wa dùn tí ara wa sì máa ń yá gágá? Ó ń jẹ́ ká mọ̀ pé ẹnì kan kíyè sí ohun tá a ṣe, ìyẹn ni pé ẹnì kan bìkítà nípa wa. Ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ pé ohun tó yẹ ká ṣe gan-an la ṣe, á sì jẹ́ ká túbọ̀ ṣe sí i lọ́jọ́ iwájú. Kò yani lẹ́nu pé gbígbóríyìn fúnni látọkànwá sábà máa ń múni sún mọ́ ẹni tó wá àkókò láti sọ ohun kan tó ń fúnni níṣìírí ọ̀hún.—Òwe 15:23.

Jésù Kristi mọ̀ pé ó ṣe pàtàkì láti gbóríyìn fúnni. Nínú àkàwé tálẹ́ńtì, ọ̀gá náà (tó jẹ́ Jésù fúnra rẹ̀) fi tọ̀yàyàtọ̀yàyà gbóríyìn fún ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn ẹrú méjèèjì tó jẹ́ olóòótọ́, nípa sísọ pé: “O káre láé, ẹrú rere àti olùṣòtítọ́!” Ẹ ò rí i pé ọ̀rọ̀ yẹn múni lọ́kàn yọ̀ gan-an! Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ò lágbára bákan náà, èrè tí wọ́n jẹ sì yàtọ̀ síra, síbẹ̀ oríyìn kan náà ni wọ́n gbà.—Mátíù 25:19-23.

Nítorí náà, ẹ jẹ́ ká máa rántí ìyá ọmọbìnrin kékeré yẹn. A ò ní láti dúró dìgbà táwọn èèyàn bá bú sẹ́kún ká tó gbóríyìn fún wọn. Dípò ìyẹn, a lè bẹ̀rẹ̀ sí fojú sílẹ̀ dáadáa ká máa wá àǹfààní tá a fi lè gbóríyìn fúnni. Láìṣe àní-àní, a nídìí gúnmọ́ láti gbóríyìn fúnni látọkànwá ní gbogbo ìgbà tí àyè rẹ̀ bá yọ.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́