ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w03 3/1 ojú ìwé 32
  • “Gbogbo Ohun Tí Mo Nílò Ni Mo Rí”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Gbogbo Ohun Tí Mo Nílò Ni Mo Rí”
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
w03 3/1 ojú ìwé 32

“Gbogbo Ohun Tí Mo Nílò Ni Mo Rí”

ÌRÒYÌN kan látọ̀dọ̀ Àjọ Ìlera Àgbáyé fojú bù ú pé kárí ayé, nǹkan bí ọgọ́fà mílíọ̀nù èèyàn ni ìdààmú ọkàn ń bá jà. Lọ́dọọdún, mílíọ̀nù kan èèyàn ló ń pa ara wọn, mílíọ̀nù mẹ́wàá sí ogún mílíọ̀nù ló sì ń gbìyànjú láti gbẹ̀mí ara wọn. Ìrànlọ́wọ́ wo làwọn tó ní ìdààmú ọkàn lè rí gbà? Ó ṣeé ṣe kí ìṣòro wọn dín kù tí wọ́n bá gba ìtọ́jú ìṣègùn, ó sì tún ṣe pàtàkì pé ká máa ṣaájò wọn. Yàtọ̀ síyẹn, àwọn kan lára àwọn tó ní ìdààmú ọkàn ti rí àfikún ìrànlọ́wọ́ gbà látinú àwọn ìwé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tá a gbé karí Bíbélì, tó sì ní ìmọ̀ràn tó wúlò, gẹ́gẹ́ bí lẹ́tà tó tẹ̀ lé e yìí láti ilẹ̀ Faransé ṣe fi hàn.

“Láìpẹ́ yìí, ilé ayé yìí sú mi. Mo wá gbàdúrà pé Ọlọ́run jọ̀ọ́ jẹ́ kí n kú. Ńṣe ló dà bíi pé mo ti kú sínú ara lọ́hùn-ún. Bí mo ṣe ń wá ìtọ́sọ́nà, mo gbàdúrà kíkankíkan sí Jèhófà. Bákan náà, mo pinnu láti ka ìwé ọdọọdún náà 2002 Yearbook of Jehovah’s Witnesses mo sì kà á tán láàárín ọjọ́ mẹ́ta. Ká sòótọ́, ìwé yẹn gbà mí níyànjú gan-an ni, ó sì fún ìgbàgbọ́ mi lókun.

“Mo tún ṣe ìwádìí pẹ̀lú nínú ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ àti Jí! ohun tí mo sì ṣàwárí yà mí lẹ́nu gan-an! Ó ju ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lọ tí mo ti ń ka ìwé ìròyìn wọ̀nyí déédéé o, ṣùgbọ́n mi ò mọ̀ pé àwọn àpilẹ̀kọ inú wọn máa ń gbani níyànjú, pé ó sì ń gbéni ró bẹ́ẹ̀. Ìfẹ́ tó ṣọ̀wọ́n gidigidi lóde òní kún inú wọn bámúbámú. Gbogbo ohun tí mo nílò ni mo rí níbẹ̀.”

Bíbélì sọ pé: “Jèhófà sún mọ́ àwọn oníròbìnújẹ́ ní ọkàn-àyà; ó sì ń gba àwọn tí a wó ẹ̀mí wọn palẹ̀ là.” (Sáàmù 34:18) Láìsí àní-àní, gbogbo àwọn “oníròbìnújẹ́ ní ọkàn-àyà” tàbí àwọn “tí a wó ẹ̀mí wọn palẹ̀” lè rí ọ̀rọ̀ ìyànjú àti ìrètí pé ọ̀la ń bọ̀ wá dáa gbà nínú Bíbélì. Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń pín àwọn ìwé tá a gbé karí Bíbélì fún àwọn èèyàn kí ó lè mú káwọn tó níṣòro jàǹfààní látinú orísun ìtùnú tí Ọlọ́run mí sí yìí.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́