ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w07 8/1 ojú ìwé 32
  • Ǹjẹ́ o Mọ̀ Pé Ọlọ́run Ń wò Ọ́?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ o Mọ̀ Pé Ọlọ́run Ń wò Ọ́?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
w07 8/1 ojú ìwé 32

Ǹjẹ́ o Mọ̀ Pé Ọlọ́run Ń wò Ọ́?

ṢÉ JÈHÓFÀ tó jẹ́ Àgbà Olùṣẹ̀dá, lágbára láti rí nǹkan? Bẹ́ẹ̀ ni, ó lágbára láti rí i! Bíbélì sọ bọ́rọ̀ ṣe jẹ́ gan-an, ó ní: “Ẹni tí ó ṣẹ̀dá ojú, ṣé kò lè rí ni?” (Sáàmù 94:9) Agbára tí Jèhófà ní láti rí nǹkan ju ti àwa ẹdá èèyàn lọ fíìfíì. Kì í kàn ṣe pé ó ń wo ìrísí wa nìkan, àmọ́ òun tún ni “olùṣàyẹ̀wò àwọn ọkàn-àyà,” ó sì lágbára láti “díwọ̀n àwọn ọkàn-àyà.” (Òwe 17:3; 21:2) Àní sẹ́, Jèhófà lágbára láti mọ ohun tá à ń rò, ohun tó ń sún wa ṣe nǹkan àti ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.

Jèhófà mọ àwọn ìṣòro tá a lè bá pàdé, ó sì máa ń dáhùn àwọn ẹ̀bẹ̀ wa. Ọ̀kan lára àwọn tó kọ sáàmù sọ pé: “Ojú Jèhófà ń bẹ lọ́dọ̀ àwọn olódodo, etí rẹ̀ sì ṣí sí igbe wọn fún ìrànlọ́wọ́. Jèhófà sún mọ́ àwọn oníròbìnújẹ́ ní ọkàn-àyà; Ó sì ń gba àwọn tí a wó ẹ̀mí wọn palẹ̀ là.” (Sáàmù 34:15, 18) Ó mà tù wá nínú o, láti mọ̀ pé Jèhófà mọ àwọn ohun tó ń bá wa fínra, ó sì máa ń gbọ́ àwọn àdúrà tá a bá gbà látọkàn wá!

Kò sí ohunkóhun tá à ń ṣe tí Jèhófà Ọlọ́run ò mọ̀ títí kan èyí tá a ṣe níkọ̀kọ̀. Àní sẹ́, “ohun gbogbo wà ní ìhòòhò àti ní ṣíṣísílẹ̀ gbayawu fún ojú ẹni tí a óò jíhìn fún.” (Hébérù 4:13) Nítorí náà, bóyá a ṣe ohun tó tọ́ tàbí ohun tí kò tọ́, Ọlọ́run rí gbogbo ẹ̀ pátá. (Òwe 15:3) Bí àpẹẹrẹ, Jẹ́nẹ́sísì 6:8, 9 sọ pé “Nóà rí ojú rere ní ojú Jèhófà” ó sì “bá Ọlọ́run tòótọ́ rìn.” Láìsí àní-àní, Nóà rí ojú rere Jèhófà, ó sì tún rí ìbùkún gbà, ìdí rẹ̀ sì ni pé ó ṣègbọràn, ó sì gbé ìgbésí ayé rẹ̀ lọ́nà tó bá ìlànà òdodo Ọlọ́run mú. (Jẹ́nẹ́sísì 6:22) Àwọn èèyàn ayé ìgbà Nóà ní tiwọn yàtọ̀ pátápátá, ọ̀daràn ni wọ́n, oníwà ìbàjẹ́ sì tún ni wọ́n. Kì í kúkú ṣe pé Ọlọ́run ò rí gbogbo ìwà ìbàjẹ́ yìí. Ọlọ́run “rí i pé ìwà búburú ènìyàn pọ̀ yanturu ní ilẹ̀ ayé, gbogbo ìtẹ̀sí ìrònú ọkàn-àyà rẹ̀ sì jẹ́ kìkì búburú ní gbogbo ìgbà.” Lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, Jèhófà pa àwọn èèyàn búburú yẹn run, ó sì pa Nóà àti ìdílé rẹ̀ mọ́ láàyè.—Jẹ́nẹ́sísì 6:5; 7:23.

Ṣe Jèhófà máa fojú rere wo ìwọ náà? Àní, ojú Jèhófà “ń lọ káàkiri ní gbogbo ilẹ̀ ayé láti fi okun rẹ̀ hàn nítorí àwọn tí ọkàn-àyà wọn pé pérépéré síhà ọ̀dọ̀ rẹ̀.” (2 Kíróníkà 16:9) Láìpẹ́ Jèhófà yóò tún pa àwọn ẹni ibi run kúrò lórí ilẹ̀ ayé, yóò sì dá àwọn ọlọ́kàn-tútù sí.—Sáàmù 37:10, 11.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́