ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w14 8/1 ojú ìwé 4
  • Ọlọ́run Máa Ń bójú Tó Ẹ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ọlọ́run Máa Ń bójú Tó Ẹ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Túbọ̀ Mọ Àwọn Ará, Kó O sì Máa Gba Tiwọn Rò
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • “Àwòkẹ́kọ̀ọ́ Ìṣàpẹẹrẹ” Tó Ṣe Pàtàkì Gan-an fún Wa
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
  • Jẹ́ Kí Ọlọ́run Máa Ṣamọ̀nà Rẹ Nínú Ohun Gbogbo
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Ìtùnú fún Àwọn Tó Ní Ìbànújẹ́ Ọkàn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
w14 8/1 ojú ìwé 4

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ǸJẸ́ ỌLỌ́RUN BÌKÍTÀ NÍPA RẸ?

Ọlọ́run Máa Ń bójú Tó Ẹ

“Ojú [Ọlọ́run] ń bẹ ní àwọn ọ̀nà ènìyàn, ó sì ń rí ìṣísẹ̀ rẹ̀ gbogbo.”—JÓÒBÙ 34:21.

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 4]

Bí ọjọ́ orí ọmọ bá ṣe kéré sí náà ló ṣe máa nílò àbójútó sí

ÌDÍ TÁWỌN KAN FI Ń ṢIYÈMÉJÌ: Ìwádìí kan tí wọ́n ṣe lẹ́nu àìpẹ́ yìí fi hàn pé ìṣùpọ̀ ìràwọ̀ Onírìísí Wàrà, ìyẹn Milky Way galaxy tí ayé yìí wà nínú rẹ̀ ní ohun tó ju ọgọ́rùn-ún bílíọ̀nù pílánẹ́ẹ̀tì lọ. Nígbà táwọn èèyàn wo bí ọ̀run ṣe lọ salalu, wọ́n ronú pé, ‘Kí ni Ọlọ́run Olódùmarè fẹ́ rí lára àwa èèyàn tá a rí tíntìntín lórí ilẹ̀ ayé tó kéré yìí?’

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ: Ọlọ́run ò kàn fún wa ní Bíbélì kó sì pa wá tì. Kàkà bẹ́ẹ̀, Jèhófà fi dá wa lójú pé: “Èmi yóò fún ọ ní ìmọ̀ràn pẹ̀lú ojú mi lára rẹ.”—Sáàmù 32:8.

Ẹ jẹ́ ká wo ohun tó ṣẹlẹ̀ sí obìnrin ará Íjíbítì kan tó ń jẹ́ Hágárì, ní ọgọ́rùn-ún ọdún lọ́nà ogún ṣáájú Sànmánì Kristẹni. Nígbà tí ó hùwà àrífín sí Sáráì ọ̀gá rẹ̀, Sáráì náà sì kàn án lábùkù, ni Hágárì bá sá lọ sínú aginjù. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Hágárì ṣàṣìṣe, Ọlọ́run ò pa á tì. Bíbélì sọ pé: “Áńgẹ́lì Jèhófà rí i.” Áńgẹ́lì náà sọ fún Hágárì pé: “Jèhófà ti gbọ́ nípa ṣíṣẹ́ tí a ń ṣẹ́ ọ níṣẹ̀ẹ́.” Lẹ́yìn náà, Hágárì sọ fún Jèhófà pé: ‘Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń rí ohun gbogbo.’—Jẹ́nẹ́sísì 16:4-13.

‘Ọlọ́run tó ń rí ohun gbogbo’ ń fi ìṣọ́ rẹ̀ ṣọ́ ìwọ náà. Bí àpẹẹrẹ: Ìyá onífẹ̀ẹ́ máa ń ṣọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ kéékèèké, pàápàá bọ́jọ́ orí wọn bá ṣì kéré. Torí pé bí ọjọ́ orí ọmọ bá ṣe kéré sí náà ló ṣe máa nílò àbójútó sí. Lọ́nà kan náà, Ọlọ́run máa ń bójú tó wa àgàgà nígbà tó bá dà bíi pé a ò já mọ́ nǹkan kan tá ò sí rẹ́ni fẹ̀yìn tì. Jèhófà sọ pé: “Ibi gíga àti ibi mímọ́ ni ibi tí mo ń gbé, àti pẹ̀lú ẹni tí a tẹ̀ rẹ́, tí ó sì rẹ̀wẹ̀sì ní ẹ̀mí, láti mú ẹ̀mí àwọn ẹni rírẹlẹ̀ sọ jí àti láti mú ọkàn-àyà àwọn tí a tẹ̀ rẹ́ sọ jí.”—Aísáyà 57:15.

Síbẹ̀, o lè máa ṣe kàyéfì pé: ‘Báwo ni Ọlọ́run ṣe ń bójú tó mi? Ṣé Ọlọ́run mọ irú ẹni tí mo jẹ́ nínú lọ́hùn-ún, àbí ìrísí mi nìkan ló máa ń wò?’

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́