ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 6/1 ojú ìwé 6-7
  • Ibi Tí Òye Àwọn Onímọ̀ Sáyẹ́ǹsì Mọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ibi Tí Òye Àwọn Onímọ̀ Sáyẹ́ǹsì Mọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àǹfààní Tí Ìmọ̀ Sáyẹ́ǹsì Ń Ṣe fún Wa
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Báwo Ni Àgbáálá Ayé àti Ìwàláàyè Ṣe Bẹ̀rẹ̀?
    Jí!—2002
  • Mímú Ìmọ̀ Sáyẹ́ǹsì àti Ìsìn Ṣọ̀kan
    Jí!—2002
  • Báwo Ni O Ṣe Lè Gbẹ́kẹ̀ Lé Sáyẹ́ǹsì Tó?
    Jí!—1998
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 6/1 ojú ìwé 6-7
Onímọ̀ sáyẹ́ǹsì kan ń ṣe ìwádìí

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ṢÉ ÌMỌ̀ SÁYẸ́ǸSÌ TI RỌ́PÒ BÍBÉLÌ?

Ibi Tí Òye Àwọn Onímọ̀ Sáyẹ́ǹsì Mọ

Lẹ́nu àìpẹ́ yìí, wọ́n tẹ àwọn ìwé kan jáde. Àwọn ìwé náà ṣàlàyé èrò àwọn tó gbà pé kò sí Ọlọ́run. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló fẹ́ ka ìwé yìí. Ìwé náà sì ti dá àríyànjiyàn ńlá sílẹ̀ nípa bóyá Ọlọ́run wà tàbí kò sí. David Eagleman tó jẹ́ onímọ̀ nípa iṣan ara sọ nípa ìwé náà pé, èrò àwọn kan lára àwọn tó ka ìwé náà ni pé àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì ti mọ gbogbo nǹkan tán. Ó wá fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì tó mọṣẹ́ wọn níṣẹ́ kì í ro ara wọn ju bó ṣe yẹ lọ. Iṣẹ́ wọn sì máa ń jẹ́ kí wọ́n ṣàwárí àwọn nǹkan tuntun tó máa ń yani lẹ́nu.

Onímọ̀ nípa sánmà kan ń lo awò tí wọ́n fi ń wo ọ̀nà jíjìn

Ọjọ́ pẹ́ tí àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì tó mọ́ṣẹ́ dunjú ti máa ń ṣèwádìí nípa àwọn nǹkan tó jẹ́ àwámáàrídìí nínú ayé. Lọ́pọ̀ ìgbà, ohun tí wọ́n rí máa ń yani lẹ́nu. Àmọ́ ṣá o, àwọn kan lára wọn máa ń ṣe àṣìṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìwádìí náà. Bí àpẹẹrẹ, Isaac Newton jẹ́ ọ̀kan lára àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì tó mọṣẹ́ jù lọ. Òun ló sọ bí agbára òòfà ṣe ń mú kí àwọn pílánẹ́ẹ̀tì, ìràwọ̀ àti àwọn ìṣùpọ̀ ìràwọ̀ wà pa pọ̀, tí wọn ò sì kọlu ara wọn. Òun náà ló ṣàwárí ẹ̀ka ìṣirò kan tí wọ́n fi ń ṣe kọ̀ǹpútà, ìyẹn calculus. Ẹ̀ka ìṣirò yìí náà ni àwọn tó ń rìnrìn àjò lójú òfúrufú máa ń lò, àwọn onímọ̀ nípa átọ́ọ̀mù náà sì ń lò ó. Ṣùgbọ́n Newton tún lọ́wọ́ sí ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ kan tí wọ́n ń pè ní alchemy, tó ní í ṣe pẹ̀lú wíwo ìràwọ̀ àti idán pípa, torí pé ó ń wá bó ṣe lè sọ irin lásán di góòlù.

Onímọ̀ nípa sánmà kan wà tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ptolemy. Ọmọ ilẹ̀ Gíríìsì ni. Ó gbé ayé ní ohun tó lé ní ẹgbẹ̀rún kan ààbọ̀ [1,500] ọdún kí wọ́n tó bí Newton. Ojú lásán ni ọ̀gbẹ́ni yìí fi ṣàyẹ̀wò àwọn ohun tó wà lójú sánmà. Ó máa ń tọpasẹ̀ àwọn ìràwọ̀ tó wà lójú sánmà lọ́wọ́ alẹ́. Bákan náà, ó mọ̀ nípa yíya àwòrán ilẹ̀ gan-an. Àmọ́, ó gbà pé ààrín ni ayé yìí wà, tí oòrùn, òṣùpá àtàwọn ìràwọ̀ sì ń yípo rẹ̀. Carl Sagan tó jẹ́ onímọ̀ nípa sánmà sọ pé, ẹgbẹ̀rún kan ààbọ̀ [1,500] ọdún gbáko ni àwọn èèyàn fi gba èrò tí kò tọ́ tí Ptolemy ní yìí gbọ́. Èyí fi hàn pé, èèyàn jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n kò túmọ̀ sí pé kò lè ṣe àṣìṣe tó bùáyà.

Onímọ̀ sáyẹ́ǹsì kan ń ka Bíbélì

Lónìí, kì í ṣe gbogbo ohun tí àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì sọ ni èèyàn lè gbára lé. Ǹjẹ́ wọ́n tiẹ̀ lè ṣe àlàyé tó kún rẹ́rẹ́ nípa ilẹ̀ ayé àti ìsálú ọ̀run? Ká sòótọ́, ìtẹ̀síwájú ti bá ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì, àǹfààní tó sì ń ṣe wá kúrò ní kèrémí. Àmọ́, ó ṣe pàtàkì ká mọ̀ pé kì í ṣe gbogbo nǹkan làwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì lè ṣe. Paul Davies tó jẹ́ onímọ̀ nípa físíìsì sọ pé: “Àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì kò lè ṣe àlàyé tó kún rẹ́rẹ́ nípa ilẹ̀ ayé àti ìsálú ọ̀run, kí àlàyé náà sì bára mu délẹ̀délẹ̀.” Òótọ́ ọ̀rọ̀ tí kò ṣe é já ní koro ni ọ̀gbẹ́ni yìí sọ. Ìyẹn ni pé: Àwa èèyàn kò lè mọ gbogbo nǹkan nípa ayé àti ìsálú ọ̀run láéláé. Fún ìdí yìí, tí àwọn èèyàn kan bá sọ pé àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì lè ṣàlàyé nípa gbogbo nǹkan tó wà lọ́run àti láyé, kò yẹ ká gbára lé irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ pátápátá.

Láìsí àní-àní, Bíbélì fún wa ní ohun tí àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì kò lè fún wa

Bíbélì sọ nípa àwọn nǹkan àgbàyanu tó wà lọ́run àti láyé pé: “Wò ó! Ìwọ̀nyí jẹ́ bèbè àwọn ọ̀nà [Ọlọ́run], àhegbọ́ mà ni ohun tí a sì gbọ́ nípa rẹ̀!” (Jóòbù 26:14) Ọ̀kẹ́ àìmọye nǹkan ló ṣì wà táwa èèyàn ò mọ, tó jẹ́ pé ó kọjá ìrònú àti òye ẹ̀dá. Kò sí àní-àní pé, ọ̀rọ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún méjì [2,000] ọdún sẹ́yìn ṣì jẹ́ òótọ́ títí dòní. Ó sọ pé: “Ìjìnlẹ̀ àwọn ọrọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run mà pọ̀ o! Àwọn ìdájọ́ rẹ̀ ti jẹ́ àwámáridìí tó, àwọn ọ̀nà rẹ̀ sì ré kọjá àwákàn!”—Róòmù 11:33.

Ìtọ́sọ́nà Tí Àwọn Onímọ̀ Sáyẹ́ǹsì Kò Lè Fún Wa

Àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì máa ń pèsè ìsọfúnni nípa ilẹ̀ ayé, àmọ́ Bíbélì nìkan ló lè fún wa ní ìlànà àti ìtọ́sọ́nà tó máa jẹ́ ká ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú àwọn ẹlòmíì, ká láyọ̀, kí ìgbésí ayé wa sì tòrò. Wo àwọn àpẹẹrẹ yìí.

  • Ọwọ́ kan tí wọ́n fi ṣe àmì dúró

    Dídènà Ìwà Ọ̀daràn

    Jẹ́ kí ẹ̀mí èèyàn jọ ẹ́ lójú

    “Ìwọ kò gbọ́dọ̀ ṣìkà pànìyàn.” —Ẹ́kísódù 20:13.

    “Olúkúlùkù ẹni tí ó bá kórìíra arákùnrin rẹ̀ jẹ́ apànìyàn.” —1 Jòhánù 3:15.

    Jẹ́ ẹlẹ́mìí àlááfíà

    “Yí padà kúrò nínú ohun búburú, kí o sì máa ṣe ohun rere; máa wá ọ̀nà láti rí àlàáfíà, kí o sì máa lépa rẹ̀.”—Sáàmù 34:14.

    “Èso òdodo ni a ń fún irúgbìn rẹ̀ lábẹ́ àwọn ipò tí ó kún fún àlàáfíà fún àwọn tí ń wá àlàáfíà.”—Jákọ́bù 3:18.

    Má ṣe hùwà jàgídíjàgan

    “Jèhófà tìkára rẹ̀ ń ṣàyẹ̀wò olódodo àti ẹni burúkú, dájúdájú, ọkàn rẹ̀ kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá nífẹ̀ẹ́ ìwà ipá.”—Sáàmù 11:5.

    “Má ṣe ìlara ọkùnrin oníwà ipá, bẹ́ẹ̀ ni kí o má yan èyíkéyìí nínú àwọn ọ̀nà rẹ̀. Nítorí oníbékebèke jẹ́ ohun ìṣe-họ́ọ̀-sí lójú Jèhófà.”—Òwe 3:31, 32.

  • Ìdílé kan

    Bí Ìdílé Ṣe Lè Láyọ̀

    Gbọ́ràn sí àwọn òbí rẹ lẹ́nu

    “Ẹ̀yin ọmọ, ẹ jẹ́ onígbọràn sí àwọn òbí yín ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Olúwa, nítorí èyí jẹ́ òdodo: ‘Bọlá fún baba rẹ àti ìyá rẹ’; èyí tí í ṣe àṣẹ kìíní pẹ̀lú ìlérí: ‘Kí nǹkan lè máa lọ dáadáa fún ọ, kí ìwọ sì lè wà fún àkókò gígùn lórí ilẹ̀ ayé.’”—Éfésù 6:1-3.

    Kọ́ àwọn ọmọ rẹ dáadáa

    “Ẹ má ṣe máa sún àwọn ọmọ yín bínú, ṣùgbọ́n ẹ máa bá a lọ ní títọ́ wọn dàgbà nínú ìbáwí àti ìlànà èrò orí Jèhófà.” —Éfésù 6:4.

    “Ẹ má ṣe máa dá àwọn ọmọ yín lágara, kí wọ́n má bàa soríkodò.”—Kólósè 3:21.

    Nífẹ̀ẹ́ ọkọ tàbí aya rẹ, kó o sì bọ̀wọ̀ fún un

    “Kí olúkúlùkù yín lẹ́nì kọ̀ọ̀kan máa nífẹ̀ẹ́ aya rẹ̀ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe nífẹ̀ẹ́ ara rẹ̀; ní ọwọ́ kejì ẹ̀wẹ̀, kí aya ní ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀ fún ọkọ rẹ̀.”—Éfésù 5:33.

  • Igi kan

    Ìmọ́tótó àyíká

    Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa àwọn tó ń ba àyíká jẹ́ nígbà ayé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì àtijọ́ pé: “A ti sọ ilẹ̀ náà gan-an di eléèérí lábẹ́ àwọn olùgbé rẹ̀, . . . a sì ka àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ sí ẹlẹ́bi.” (Aísáyà 24:5, 6) Ọlọ́run máa fìyà jẹ gbogbo àwọn ẹni ibi tó ń ba ilẹ̀ ayé jẹ́. Bíbélì sọ pé Ọlọ́run máa “run àwọn tí ń run ilẹ̀ ayé.” (Ìṣípayá 11:18) Wọn kò ní lọ láìjìyà ìwà ìbàjẹ́ wọn.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́