ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 9/1 ojú ìwé 4
  • Irú Èèyàn Wo ni Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Irú Èèyàn Wo ni Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí nìdí tá a fi ń wàásù?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Má Ṣe Dá Sí Ọ̀rọ̀ Òṣèlú Tàbí Ogun
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
  • Kí Nìdí Tí Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Kì Í Fi Í Lọ́wọ́ sí Ìṣèlú?
    Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • Ohun Tó Túmọ̀ Sí Láti Má Ṣe Dá Sí Ogun àti Ọ̀rọ̀ Òṣèlú
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 9/1 ojú ìwé 4
Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà láti onírúurú ẹ̀yà ń kí ara wọn nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | TA NI ÀWỌN ẸLẸ́RÌÍ JÈHÓFÀ?

Irú Èèyàn Wo ni Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà?

Ibi gbogbo ni àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà wà kárí ayé, a ò sì dara pọ̀ mọ́ àwùjọ ẹ̀sìn èyíkéyìí. Bó tílẹ̀ jẹ́ pé orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ni orílé-iṣẹ́ wa wà, síbẹ̀ èyí tó pọ̀ jù lára àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ló ń gbé ní àwọn orílẹ̀-èdè míì. Kódà, a ti lẹ́ ní mílíọ̀nù mẹ́jọ báyìí, a sì ń wàásù ní àwọn ilẹ̀ tó lé ní 230 kárí ayé. À ń tẹ̀ lé ọ̀rọ̀ Jésù tó sọ pé: “A ó sì wàásù ìhìn rere ìjọba yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí a ń gbé, láti ṣe ẹ̀rí fún gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.”​—Mátíù 24:14.

Ibi yòówù ká máa gbé, tọkàntọkàn la fi ń pa òfin ìlú mọ́. Síbẹ̀, a kì í dá sí ọ̀rọ̀ ìṣèlú. Ìdí ni pé à ń tẹ̀ lé ìtọ́ni tí Jésù fún gbogbo Kristẹni pé kí wọ́n má ṣe jẹ́ “apá kan ayé.” Torí náà, a kì í lọ́wọ́ sí ìṣèlú tàbí ọ̀ràn ogun. (Jòhánù 15:19; 17:16) Nígbà Ogun Àgbáyé Kejì, wọ́n ti àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà mọ́lé, wọ́n fìyà jẹ àwọn kan nínú wọn, wọ́n sì pa àwọn míì. Ìdí sì ni pé wọn ò dá sí ọ̀ràn ogun. Ẹnì kan tó jẹ́ bíṣọ́ọ̀bù nílẹ̀ Jámánì nígbà kan sọ pé: “Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà níkàn ló lè fọwọ́ sọ̀yà pé àwọn ò dá sí ọ̀ràn ogun nígbà ìjọba Násì.”

“[Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà] ní ìwà ọmọlúwàbí. Wọn kì í ṣe onímọtara-ẹni-nìkan, torí náà irú wọn là ń fẹ́ kó di ipò pàtàkì mu láwùjọ. Àmọ́, wọn ò ní ṣe bẹ́ẹ̀ láé. . . . Wọ́n bọ̀wọ̀ fún àwọn aláṣẹ, àmọ́ wọ́n gbà pé Ìjọba Ọlọ́run nìkan ló lè yanjú gbogbo ìṣòro àwa èèyàn.”​—Ìwé ìròyìn Nová Svoboda, lórílẹ̀-èdè Czech Republic.

Àmọ́ ṣá, kì í ṣe pé à ń dá tara wa ṣe o. Jésù gbàdúrà sí Ọlọ́run nípa àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé: “Èmi kò béèrè pé kí o mú wọn kúrò ní ayé.” (Jòhánù 17:15) Torí náà, wàá rí i pé a máa ń lọ sí ibiṣẹ́, a máa ń lọ sí ọjà, a sì máa ń lọ sí ilé ìwé pẹ̀lú àwọn èèyàn tó wà níbi tá a bá ń gbé.

ÀWỌN ILẸ̀ TÍ ÀWA ẸLẸ́RÌÍ JÈHÓFÀ PỌ̀ SÍ

  • Amẹ́ríkà 1,190,000

  • Mẹ́síkò 800,000

  • Brazil 770,000

  • Nàìjíríà 330,000

  • Ítálì 250,000

  • Japan 220,000

Ìlú Ísírẹ́lì òde òní

Wo fídíò yìí, Special Convention in Israel lórí ìkànnì www.jw.org. Nínú fídíò náà, wàá rí bí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà lórílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì àti Palẹ́sínì kò ṣe gba ẹ̀mí kẹ́lẹ́yàmẹ̀yà láyè láàárín wọn. (wo abẹ́ ABOUT US > CONVENTIONS)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́