Àwọn Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Ìròyìn Yìí
3 Wọ́n Yọ̀ǹda Ara Wọn Tinútinú—Ní Gánà
Ọ̀SẸ̀ AUGUST 29, 2016–SEPTEMBER 4, 2016
7 Máa Wá Ìjọba Ọlọ́run, Má Ṣe Wá Àwọn Nǹkan
Jésù kọ́ wa pé Ìjọba Ọlọ́run ló yẹ ká kọ́kọ́ máa wá, kì í ṣe àwọn nǹkan. Kí la lè ṣe tá ò fi ní máa kó ohun ìní jọ? Báwo la ṣè lè jẹ́ kí ohun ìní díẹ̀ tẹ́ wa lọ́rùn ká lè máa ṣe púpọ̀ sí i nínú ìjọsìn wa? Ẹ jẹ́ ká jíròrò àwọn ìmọ̀ràn Jésù nínú Ìwàásù Lórí Òkè bó ṣe wà lákọọ́lẹ̀ nínú Mátíù 6:25-34.
Ọ̀SẸ̀ SEPTEMBER 5-11, 2016
13 Kí Nìdí Tá A Fi Gbọ́dọ̀ Máa Ṣọ́nà?
Torí pé Kristẹni ni wá, ó yẹ ká fọwọ́ gidi mú ìmọ̀ràn Jésù tó sọ pé “ká máa ṣọ́nà” láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí. (Mát. 24:42) Ká lè máa ṣọ́nà, ó ṣe pàtàkì pé ká má ṣe fàyè gba àwọn ohun tó máa ń mú kéèyàn dẹra nù, débi pé a ò ní wà lójúfò mọ́ pé Jésù ń bọ̀. Àpilẹ̀kọ yìí á jẹ́ ká mọ bí a ṣe lè máa wà lójúfò tá ò sì ní ní ìpínyà ọkàn.
18 “Má Fòyà. Èmi Fúnra Mi Yóò Ràn Ọ́ Lọ́wọ́”
Ọ̀SẸ̀ SEPTEMBER 12-18, 2016
21 A Mọyì Inú Rere Àìlẹ́tọ̀ọ́sí Tí Ọlọ́run Ń Fi Hàn sí Wa
Ọ̀SẸ̀ SEPTEMBER 19-25, 2016
26 Ẹ Jẹ́ Kí Aráyé Gbọ́ Ìhìn Rere Nípa Inú Rere Àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run
Àpilẹ̀kọ méjèèjì yìí jíròrò àwọn ọ̀nà tí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Jèhófà gbà ń ṣe wá láǹfààní. Wọ́n tún jẹ́ ká mọ ìdí tó fi yẹ ká mọyì inú rere Jèhófà ká sì tipa bẹ́ẹ̀ jẹ́ káwọn èèyàn mọ ọ̀nà táwọn náà á gbà jàǹfààní inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí rẹ̀.