ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 12/95 ojú ìwé 8
  • Mímúra Sílẹ̀ fún Ìpadàbẹ̀wò Tí Ó Gbéṣẹ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Mímúra Sílẹ̀ fún Ìpadàbẹ̀wò Tí Ó Gbéṣẹ́
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1995
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1995
km 12/95 ojú ìwé 8

Mímúra Sílẹ̀ fún Ìpadàbẹ̀wò Tí Ó Gbéṣẹ́

1 Jesu sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Nitori naa ẹ lọ kí ẹ sì máa sọ awọn ènìyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ-ẹ̀yìn, . . . ẹ máa kọ́ wọn lati máa pa gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún yín mọ́.” (Matt. 28:19, 20) A ń ṣàṣeparí kíkọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn tuntun nípa ṣíṣe ìpadàbẹ̀wò àti dídarí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bibeli. Ó ṣeé ṣe pé àwọn tí ó fìfẹ́ hàn nínú ìwé Ọkunrin Titobilọla, nígbà tí o kọ́kọ́ ké sí wọn, yóò láyọ̀ láti tún rí ọ. Bí o bá wéwèé ṣáájú, tí o múra sílẹ̀ dáadáa, tí o sì ṣètò láti ṣèpadàbẹ̀wò tí ó gbéṣẹ́, ó lè ṣeé ṣe fún ọ láti bẹ̀rẹ̀, kí o sì darí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bibeli inú ilé déédéé.

2 Bí o bá ti sọ̀rọ̀ lórí ìpínrọ̀ 2 àti 3 ní ìbẹ̀rẹ̀ ìwé “Ọkunrin Titobilọla,” o lè sọ pé:

◼ “Nígbà tí mo wábí kẹ́yìn, a sọ̀rọ̀ lórí bí Jesu Kristi ṣe jẹ́ ọkùnrin títóbi lọ́lá jù lọ tí ó tíì gbé ayé rí. Àwọn ọba ńlá àti àwọn òpìtàn pẹ̀lú jẹ́rìí sí i pé Jesu ni ọkùnrin títóbi lọ́lá jù lọ tí ó tíì gbé ayé rí. Ṣùgbọ́n, kí ni ó sọ ọ́ di ọkùnrin títóbi lọ́lá jù lọ? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Jesu ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Baba rẹ̀, Ọlọrun Olódùmarè, ì bá ti ṣe. [Ka Johannu 14:9, 10.] Ṣíṣàfarawé Ọlọrun lọ́nà pípé pérépéré sọ ọ́ di ọkùnrin títóbi lọ́lá jù lọ. Ṣùgbọ́n, àwọn ànímọ́ Ọlọrun wo ni Kristi fi hàn?” Ṣí i sí ìbẹ̀rẹ̀, kí o sì gbé àwọn kókó díẹ̀ yẹ̀ wò lábẹ́ ìsọ̀rí náà, “Ohun Tí Ó Mú Kí Ó Tobilọla Julọ.” Ṣètò fún ìbẹ̀wò rẹ tí yóò tẹ̀ lé e.

3 Bí o bá padà lọ láti mú ìjíròrò lórí àkóso Jesu Kristi tẹ̀ síwájú, o lè sọ pé:

◼ “A fohùn ṣọ̀kan nínú ìjíròrò wa tí ó kọjá pé, a ti yan Jesu Kristi láti ṣàkóso ilẹ̀ ayé. Ṣùgbọ́n, èé ṣe tí Jesu yóò fi jẹ́ alákòóso tí ó dára jù lọ tí ayé lè ní? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Ó kórìíra àìṣèdájọ́ òdodo, ó sì nífẹ̀ẹ́ ohun rere. [Ka Heberu 1:9.] Nígbà tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, ó fi ohun tí yóò ṣàṣeparí gẹ́gẹ́ bí Ọba lórí ilẹ̀ ayé hàn, ní ìwọ̀n ṣékélé. Ó wo àwọn aláìsàn sàn, ó bọ́ àwọn tí ebi ń pa, ó sì tún jí àwọn òkú dìde pàápàá. Yàtọ̀ sí ìyẹn, ó tún ní agbára tí ó ju ti ẹ̀dá lọ láti kápá àwọn ìjábá. Alákòóso kankan ha wà tí ó lè faga gbága pẹ̀lú rẹ̀ bí? [Jẹ́ kí ó fèsì.] A lè kọ́ púpọ̀ sí i nípa alákòóso tí ó ju ẹ̀dá ènìyàn lọ yìí, ní orí 53.” Lẹ́yìn náà, jíròrò àwọn ìpínrọ̀ díẹ̀, kí o sì ṣèlérí láti padà wá.

4 O lè bẹ̀rẹ̀ ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ pẹ̀lú ẹnì kan tí ó nífẹ̀ẹ́ sí níní ìbátan tímọ́tímọ́ pẹ̀lú Jesu, ní ọ̀nà yìí:

◼ “Nígbà tí mo wábí kẹ́yìn, a ka Johannu 17:3. A lóye ìdí tí ó fi yẹ kí a ní ìmọ̀ pípéye, kí a baà lè ní ìbátan tímọ́tímọ́ pẹ̀lú Jesu Kristi àti Baba rẹ̀ ọ̀run. Fún àpẹẹrẹ, o ha mọ ìdí tí Jesu fi ti ọ̀run wá sí ayé bí? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Ọ̀pọ̀ yóò sọ pé, ó wá sí ayé láti rà wá padà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú. Òótọ́ ni! Ṣùgbọ́n, ìdí pàtàkì mìíràn tún wà tí Jesu fi wá sí ayé. [Ka Luku 4:42, 43.] Ó wá, ní pàtàkì láti wàásù àti láti kọ́ àwọn ẹlòmíràn nípa Ìjọba Ọlọrun.” Gbé àwọn kókó díẹ̀ ípa Ìjọba náà yẹ̀ wò, ní orí 133. Bí ó bá ṣeé ṣe, bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bibeli.

5 Bí o bá ń padà lọ sọ́dọ̀ ẹni tí o lo ọ̀nà ìgbàyọsíni tààràtà láti bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bibeli pẹ̀lú rẹ̀, o lè bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò rẹ ní ọ̀nà yìí:

◼ “Ní ìgbà tí mo ké sí ọ kẹ́yìn, a jíròrò orí 59, ‘Ta Ni Jesu Jẹ́ Niti Gidi?’ nínú ìwé Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí. Ìwọ yóò rántí pé Jesu fúnra rẹ̀ ni ó bi àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ní ìbéèrè yìí. Ìdí tí mo fi wá nísinsìnyí ni láti jíròrò apá tí ó kẹ́yìn nínú orí náà pẹ̀lú rẹ. Ó ṣí kúlẹ̀kúlẹ̀ nípa ẹni tí Jesu jẹ́ ní ti gidi payá síwájú sí i.” O lè máa bá ìjíròrò rẹ nìṣó pẹ̀lú onílé náà.

6 Lẹ́yìn tí ó ti ka ìwé náà, ẹnì kan fi ìtara sọ pé: “Òun ni ìwé tí ó dára jù lọ tí mo tíì kà rí! Ó yí ìgbésí ayé mi padà.” Ṣíṣe ìpadàbẹ̀wò tí ó gbéṣẹ́ sọ́dọ̀ àwọn tí ó fìfẹ́ hàn nínú ìwé Ọkunrin Titobilọla, lè sèso àtàtà ní ìpínlẹ̀ rẹ.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́