ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 7/00 ojú ìwé 1
  • “Àwa Kò Lè Dẹ́kun Sísọ̀rọ̀”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Àwa Kò Lè Dẹ́kun Sísọ̀rọ̀”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ Máa Fi Àìṣojo Sọ̀rọ̀ Ọlọ́run
    Jọ́sìn Ọlọ́run Tòótọ́ Kan Ṣoṣo Náà
  • ‘Máa Sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Láìṣojo’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Polongo Ìhìn Rere Láìṣojo
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • “A Gbọ́dọ̀ Ṣègbọràn sí Ọlọ́run Gẹ́gẹ́ Bí Alákòóso Dípò Èèyàn”
    “Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
km 7/00 ojú ìwé 1

“Àwa Kò Lè Dẹ́kun Sísọ̀rọ̀”

1 Jésù Kristi ń bójú tó iṣẹ́ ìwàásù náà ní kínníkínní. (Mát. 28:20; Máàkù 13:10) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó mílíọ̀nù mẹ́fà àwọn olùpòkìkí aláápọn tí wọ́n ń jẹ́rìí ní ilẹ̀ igba ó lé mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, a ò gbọ́dọ̀ ronú pé iṣẹ́ ìjẹ́rìí wa ti parí. Títí di ìgbà tí Ọlọ́run yóò fi kéde pé iṣẹ́ náà ti parí, “àwa kò lè dẹ́kun sísọ̀rọ̀” nípa àwọn ohun tí a ti kọ́.—Ìṣe 4:20.

2 Gbára Lé Ẹ̀mí Ọlọ́run: Sátánì máa ń sapá gidigidi láti mú ká rẹ̀wẹ̀sì. (Ìṣí. 12:17) Ẹran ara aláìpé wa tún ń kó ọ̀pọ̀ ìṣòro bá wa. Irú àwọn nǹkan báyẹn lè yí àfiyèsí wa kúrò nínú iṣẹ́ ìwàásù tó ṣe pàtàkì jù lọ yìí. Ṣùgbọ́n, bí a bá gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, ẹ̀mí rẹ̀ yóò ràn wá lọ́wọ́ láti kojú ohun ìdènà èyíkéyìí.

3 Nígbà tí wọ́n ṣenúnibíni lílekoko sí ìjọ Kristẹni ọ̀rúndún kìíní, àwọn ará gbàdúrà sí Ọlọ́run pé kí ó ran àwọn lọ́wọ́ láti lè máa fi àìṣojo gbogbo sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀. Jèhófà dáhùn àdúrà wọn, ó fún wọn ní ẹ̀mí rẹ̀, ó sì fún wọn ní ìtara àti ìmúratán tí wọ́n nílò láti máa wàásù nìṣó. Nítorí èyí, wọ́n ń bá a nìṣó láìdábọ̀ ní fífi àìṣojo polongo ìhìn rere náà.—Ìṣe 4:29, 31; 5:42.

4 Má Ṣe Bẹ̀rù Ọ̀rọ̀ Amúnirẹ̀wẹ̀sì: Ohun tí ọ̀pọ̀ èèyàn ń rò nípa wa tàbí ọ̀rọ̀ èké tí wọ́n fi ń bà wá jẹ́ lè fẹ́ mú wa ṣojo. Ṣùgbọ́n, rántí gbólóhùn aláìṣojo tí Pétérù àti àwọn àpọ́sítélì yòókù sọ níwájú Sànhẹ́dírìn, bó ṣe wà lákọọ́lẹ̀ ní Ìṣe 5:29-31. Gẹ́gẹ́ bí Gàmálíẹ́lì tó jẹ́ olùkọ́ Òfin ṣe sọ, iṣẹ́ Ọlọ́run ò ṣeé bì wó. Kì í ṣe agbára wa la fi ń ṣe é. Ọlọ́run ló ń ti iṣẹ́ bàǹtàbanta yìí lẹ́yìn, òun nìkan ló sì lè ṣe é láṣeparí!—Sek. 4:6.

5 Ẹ jẹ́ kí á máa bẹ Jèhófà lójoojúmọ́ pé kí ẹ̀mí rẹ̀ máa ràn wá lọ́wọ́ kí a lè máa fi ìtara polongo ìhìn rere náà. Ǹjẹ́ kí a lè sọ bí Jeremáyà ti sọ pé ṣe ni ìhìn Ìjọba náà dà bí iná tí ń jó nínú egungun wa. (Jer. 20:9) A ò gbọ́dọ̀ dákẹ́!

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́